Monday, 29 June 2020

ÌTUMỌ̀ TÍRÀ ÁHLÀRÍ (Ẹ̀kọ́ Kejìlá)

فَصْلٌ فِي السُجُودِ فِي سَهْوِ السُّنَنِ

وَلَا يَكُونُ السُّجُودُ الْقَبَلِيُّ إِلَّا لِتَرْكِ سُنَّتَيْنِ فَأَكْثَرَ. وَأَمَّا السُّنَّةُ الْوَاحِدَةُ فَلَا سُجُودَ لَهَا إِلَّا السِّرَّ وَالْجَهْرَ، فَمَنْ أَسَرَّ فِي الْجَهْرِ سَجَدَ قَبْلَ السَّلَامِ، وَمَنْ جَهَرَ فِي السِّرِّ سَجَدَ بَعْدَ السَّلَامِ. وَمَنْ تَكَلَّمَ سَاهِيًا سَجَدَ بَعْدَ السَّلَامِ، وَمَنْ سَلَّمَ مِنْ رَكْعَتَيْنِ سَاهِيًا سَجَدَ بَعْدَ السَّلَامِ، وَمَنْ زَادَ فِي الصَّلَاةِ رَكْعَةً أَوْ رَكْعَتَيْنِ سَجَدَ بَعْدَ السَّلَامِ. وَمَنْ زَادَ فِي الصَّلَاةِ مِثْلَهَا بَطَلَتْ، وَمَنْ شَكَّ فِي كَمَالِ صَلَاتِهِ أَتَى بِمَا شَكّ فِيهِ، وَالشَّكُّ فِي النُّقْصَانِ كَتَحَقُّقِهِ.

 

Ẹ̀kọ́ Nípa Ìforíkanlẹ̀ Ìgbàgbé Níbi Àwọn Isẹ́ tí Kìí Se Ọ̀ranyàn

 

Ìgbà tí áò mú ìforíkanlẹ̀ méjì síwájú sálámọ̀ wá níbi ìgbàgbé àwọn isẹ́ tí kìí se ọ̀ranyàn (Sunan) ni ìgbà tí ìgbàgbé láti mú méjì tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ wá nínú irúfẹ́ àwọn isẹ́ yìí sẹlẹ̀ lórí ìrun kíkí. Sùgbọ́n tí kò bá ju ẹyọkan péré lọ, kò sí ìforíkanlẹ̀ ìgbàgbé fún un àyàfi tí ó bá jẹ́ ìgbàgbé ọ̀kan nínú àwọn ìlànà ìkírun tí ó kanpá (Sunnatun Muakkadah); gẹ́gẹ́ bíi kíkéwú sókè tàbí kíkéwú jẹ́ẹ́jẹ́.

Ẹni tí ó bá kéwú sókè láyè jẹ́ẹ́jẹ́, yóò tánràn rẹ̀ pẹ̀lú ìforíkanlẹ̀ ìgbàgbé lẹ́yìn sálámọ̀. Ẹni bá wáá kéwú jẹ́ẹ́jẹ́ láyè kíké sókè, ìforíkanlẹ̀ ìgbàgbé síwájú sálámọ̀ ni yóò fi tán an.

Ẹni bá gbàgbé sọ̀rọ̀ lórí ìrun, ìtanràn rẹ̀ ni síse ìforíkanlẹ̀ ìgbàgbé lẹ́yìn sálámọ̀.

Ẹni tí ó bá gbàgbé sálámọ̀ lórí ọ̀pá méjì, ìforíkanlẹ̀ ìgbàgbé lẹ́yìn sálámọ̀ ni ìtanràn rẹ̀. Ẹni tí ó bá sì gbàgbé fi ọ̀pá kan tàbí méjì kún ìrun, òun náà yóò fi ìforíkanlẹ̀ ìgbàgbé lẹ́yìn sálámọ̀ tán an.

Ẹni tí ó bá wáá gbàgbé fi dèèdé iye ọ̀pá ìrun tí ó ń kí lọ́wọ́ kún ìrun, ìrun rẹ̀ ti bàjẹ́. Ẹni tí ó bá ń se iyè méjì lórí pípé ìrun rẹ̀ tàbí àìpé, yóò mú ọ̀pá tí iye méjì wà lórí rẹ̀ wá. 

Wednesday, 24 June 2020

ÌTUMỌ̀ TÍRÀ ÁHLÀRÍ (Ẹ̀kọ́ Kọkànlá)

بَابٌ فِي السَّهْوِ

 

وَسُجُودُ السَّهْوِ فِي الصَّلَاةِ سُنَّةٌ، فَلِلنُّقْصَانِ سَجْدَتَانِ قَبْلَ السَّلَامِ بَعْدَ تَمَامِ التَّشَهُّدَيْنِ يَزِيدُ بَعْدَهُمَا تَشَهُّدًا آخَرَ. وَلِلزِّيَادَةِ سَجْدَتَانِ بَعْدَ السَّلَامِ يَتَشَهَّدُ بَعْدَهُمَا وَيُسَلِّمُ تَسْلِيمَةً أُخْرَى. وَمَنْ نَقَصَ وَزَادَ سَجَدَ قَبْلَ السَّلَامِ. وَمَنْ نَسِيَ السُّجُودَ الْقَبَلِيَّ حَتَّى سَلَّمَ سَجَدَ إِنْ كَانَ قَرِيبًا. وَإِنْ طَالَ أَوْ خَرَجَ مِنَ الْمَسْجِدِ بَطَلَ السُّجُودُ وَتَبْطُلُ الصَّلَاةُ مَعَهُ إِنْ كَانَ عَلَى ثَلَاثِ سُنَنٍ أَوْ أَكْثَرَ مِنْ ذَلِكَ وَإِلَّا فَلَا تَبْطُلُ. وَمَنْ نَسِيَ السُّجُودَ البَعْدِيَّ سَجَدَهُ وَلَوْ بَعْدَ عَامٍ. وَمَنْ نَقَصَ فَرِيضَةً فَلَا يُجْزِيهِ السُّجُودُ عَنْهَا. وَمَنْ نَقَصَ الْفَضَائِلَ فَلَا سُجُودَ عَلَيْهِ. 

 

ÀKÒRÍ ASÀLÀYÉ NÍPA ÌFORÍKANLẸ̀ ÌGBÀGBÉ

 

Ìlànà ànábì (Muhammad) ni ìforíkanlẹ̀ ìgbàgbé níbi ìrun jẹ́. Tí ó bá jẹ́ àdínkù ìrun ni ó sẹlẹ̀, ìforíkanlẹ̀ méjì síwájú sálámọ̀ lẹ́yìn àtááyá (Taṣahudu) ìgbẹ̀yìn ni ìtanràn rẹ̀, pẹ̀lú síse àtááyá (Taṣahudu) míràn lẹ́yìn ìforínkanlẹ̀ méjéèjì síwájú sálámọ̀.

Tí ó bá wáá jẹ́ àlékún ìrun ní ó bá ìgbàgbé wá, ìforíkanlẹ̀ méjì lẹ́yìn sálámọ̀ ní ìtanràn rẹ̀, pẹ̀lú sìse àtááyá (Taṣahudu) míràn lẹ́yìn ìforíkanlẹ̀ méjéèjì, pẹ̀lú mímú sálámọ̀ míràn wá.

Ẹni tí ó bá jẹ́ wípé méjéèjì (Àdínkù àtí Àlékún) ni ó sẹlẹ̀ lórí ìrun rẹ̀, ìforíkanlẹ̀ méjì síwájú sálámọ̀ ni yóó fi tánràn rẹ̀.

Ẹni tí ó bá yẹ kí ó se ìforíkanlẹ̀ méjì síwájú sálámọ̀ tí kò ranti tí ó fi sálámọ̀, yóò mú ìforíkanlẹ̀ méjì náà wá tí àsìkò tí ó wà láàrin sálámọ̀ rẹ̀ àti ìsọyè rẹ̀ kò bá jágùn. Sùgbọ́n tí àsìkò tí ó wà láàrin méjéèjì bá fi jágùn tàbí olùkírun ti jáde ní ibùdó ìkírun (Masalasi), ìforíkanlẹ̀ méjéèjì pẹ̀lú ìrun rẹ̀ ti bàjẹ́, èyun ùn tí ó bá jẹ́ wípé oun tí ó bá igbagbe rẹ̀ rìn ni àwọn oun tí kíì se ọ̀ranyan (Sunan) mẹ́ta tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ; láì kò jẹ́ bẹ́ẹ̀, ìrun rẹ̀ kò bàjẹ́.

Ẹni tí ó bá wáá jẹ́ ìforíkanlẹ̀ ẹ̀yìn sálámọ̀ ni ó gbàgbé láti mú wá, yóò mu wá ní ìgbàkígbà tí ó bá ranti kì bá ǹjẹ́ lẹ́yìn odidi ọdún kan ni.

Tí ó bá jẹ́pé isẹ́ ọ̀ranyàn ìrun ni ó bá igbagbe rìn, ìforínkanlẹ̀ igbagbe kò ràn án, àyàfi kí ó mú isẹ́ ọ̀ranyàn náà wá padà.

Tí ó bá sì jẹ́ wípé oun tí ó bá ìgbàgbé rìn ni ọ̀kan nímú àwọn oun tí wọ́n kàn fẹ́ síse wọ́n lórí ìrun, ìforíkanlẹ̀ ìgbàgbé kíì se ọ̀ranyàn láti mú wá.

Wednesday, 17 June 2020

ÌTUMỌ̀ TÍRÀ ÁHLÀRÍ (Ẹ̀kọ́ Kẹ̀wá)

فَصْلٌ فِي قَضَاءِ الصَّلاةِ


 يَجِبُ قَضَاءُ مَا فِي الذِّمَّةِ مِنْ الصَّلَوَاتِ وَلَا يَحِلُّ التَّفْرِيطُ فِيهَا. وَمَنْ صَلَّى كُلَّ يَوْمٍ خَمْسَةَ أَيَّامٍ فَلَيْسَ بِمُفَرِّطٍ. وَيَقْضِيهَا عَلَى نَحْوِ مَا فَاتَتْهُ، إِنْ كَانَتْ حَضَرِيَّةً قَضَاهَا حَضَرِيَّةً. وَإِنْ كَانَتْ سَفَرِيَّةً قَضَاهَا سَفَرِيَّةً سَوَاءٌ كَانَ حِينَ الْقَضَاءِ فِي حَضَرٍ أَوْ سَفَرٍ. وَالتَّرْتِيبُ بَيْنَ الْحَاضِرَتَيْنِ وَبَيْنَ يَسِيرِ الْفَوَائِتِ مَعَ الْحَاضِرَةِ وَاجِبٌ مَعَ الذِّكْرِ. وَالْيَسِيرُ أَرْبَعُ صَلَوَاتٍ فَأَدْنَى، وَمَنْ كَانَتْ عَلَيْهِ أَرْبَعُ صَلَوَاتٍ فَأَقَلُّ صَلَّاهَا قَبْلَ الْحَاضِرَةِ وَلَوْ خَرَجَ وَقْتُهَا، وَيَجُوزُ الْقَضَاءُ فِي كُلِّ وَقْتٍ. وَلَا يَتَنَفَّلُ مَنْ عَلَيْهِ الْقَضَاءُ وَلَا يُصَلِّي الضُّحَى وَلَا قِيَامَ رَمَضَانَ وَلَا يَجُوزُ لَهُ إِلَّا الشَّفْعُ وَالْوَتْرُ وَالْفَجْرُ وَالْعِيدَانِ وَالْخُسُوفُ وَالِاسْتِسْقَاءُ. وَيَجُوزُ لِمَنْ عَلَيْهِمُ الْقَضَاءُ أَنْ يُصَلُّوا جَمَاعَةً إِذَا اسْتَوَتْ صَلَاتُهُمْ. وَمَنْ نَسِيَ عَدَدَ مَا عَلَيْهِ مِنْ الْقَضَاءِ صَلَّى عَدَدًا لَا يَبْقَى مَعَهُ شَكٌّ.

 

Ẹ̀kọ́ Nípa Sísan Gbèsè Ìrun


Ọ̀ranyàn ni fún ẹni tí ó bá jẹ gbèsè ìrun kí ó san án láì kò fi jáfara. Ẹni tí ó bọ́ níbi fífi gbèsè ìrun jáfara ni ẹni tí ó bá sapá san gbèsè odidi ìrun ọjọ́ máàrún ní ọjọ́ kan.


Dèèdé ìrun tí onígbèsè ìrun bá sì jẹ ni yóò san; bí ó bá jẹ́ gbèsè ìrun onílé ni ó jẹ, ìsan onílé náà ni yóó san àn, bí ó bá sì jẹ́ gbèsè ìrun arìnrìn àjò náà ni ó jẹ, ìsan arìnrìn àjò náà ni yóò san án, yálà àjò ni sísan gbèsè ìrun onílé bá a ni tàbí ilé ni sísan gbèsè ìrun arìnrìn àjò bá a.


Sísan gbèsè ìrun méjì (tí ó tò tẹ̀lé ara wọn lẹ́yìn tí àsìkò wọn ti jáde, àti ìrun méjì tí kò pẹ́jù tí àsìkò ọ̀kan nínú wọn ti jáde tí ìkejì kò tíì jáde) ní tẹ̀létẹ̀lé jẹ́ ọ̀ranyàn, lópin ìgbà tí ìgbàgbé kò bá se olùjẹ gbèsè ìrun.


Òdiwọ̀n gbèsè tí kò pọ̀jù ni ọ̀pá ìrun mẹ́rin wálẹ̀. Ẹni tí ó bá ní gbèsè ọ̀pá ìrun mẹ́rin wálẹ̀ lọ́rùn gbudọ̀ sán síwájú ìrun tí àsìkò rẹ̀ wà níta, kódà kí àsìkò ìrun tí ó wà níta jáde síwájú kí ó tóó san án tán. Ìgbàkígbà sì ni sísan gbèsè ìrun lẹ́tọ́, yálà ní ọ̀sán tàbí òru.


Kò sì lẹ́tọ́ fún ẹni tí ó bá ní gbèsè ìrun lọ́rùn kí ó máa kí ìrun àkígbọrẹ (Naafila); bíi naafila ìyálẹ̀ta (Duhaa), naafila òru osù ààwẹ ramalaana (Áásámú). Àyàfi àkígbọrẹ (Nááfílà) oníméjìméjì (Ṣáfúì) àti ẹlẹ́yọkọ̀ọ̀kan (Wítìrí) tí a máá ń yàn lóru, nááfílà ọ̀pá méjì ẹ̀yìn àlùfájàrí, ìrun ọdún méjéèjì (Ìtunu àti Iléyá), nááfílà ìtọrọ àánú Ọlọ́hun nígbà tí ìmọ́lẹ̀ òòrùn bá wọlé (Khusuufu), àti nááfílà tí ìtọrọ omi òjò lọ́dọ̀ Ọlọ́hun lásìkò ọ̀dá (Istiskọọu).


Kòsì burú kí àwọn èèyàn púpọ̀ tí gbèsè wọn papọ̀ san gbèsè wọn ní àpapọ̀ (Jànmọ́ ọ̀n).


Ẹni tí ìgbàgbé iye gbèsè wákàtí ìrun tí ó jẹ sọ́rùn bá wáá se, iye wákàtí tí ó le gbé ìrújú kúrò fun ni yóó san.


Saturday, 13 June 2020

ÌTUMỌ̀ TÍRÀ ÁHLÀRÍ (Ẹ̀kọ́ Kẹsan)

فَصْلٌ فِي أَحْوَالِ أَدَاءِ الصَّلاةِ

لِلصَّلَاةِ الْمَفْرُوضَةِ سَبْعَةُ أَحْوَالٍ مُرَتَّبَةٍ تُؤَدَّى عَلَيْهَا. أَرْبَعَةٌ مِنْهَا عَلَى الْوُجُوبِ، وَثَلَاثَةٌ عَلَى الِاسْتِحْبَابِ. أَوَّلُهَا الْقِيَامُ بِغَيْرِ اسْتِنَادٍ ثُمَّ الْقِيَامُ بِاسْتِنَادٍ، ثُمَّ الْجُلُوسُ بِغَيْرِ اسْتِنَادٍ، ثُمَّ الْجُلُوسُ بِاسْتِنَادٍ، فَالتَّرْتِيبُ بَيْنَ هَذِهِ الْأَرْبَعَةِ عَلَى الْوُجُوبِ إِذَا قَدَرَ عَلَى حَالَةٍ مِنْهَا وَصَلَّى بِحَالَةٍ دُونَهَا بِطَلَتْ صَلَاتُه. وَالثَّلَاثَةُ الَّتِي عَلَى الِاسْتِحْبَابِ هِيَ: أَنْ يُصَلِّيَ الْعَاجِزُ عَنْ هَذِهِ الثَّلَاثَةِ الْمَذْكُورَةِ عَلَى جَنْبِهِ الْأَيْمَنِ، ثُمَّ عَلَى الْأَيْسَرِ ثُمَّ عَلَى ظَهْرِهِ. فَإِنْ خَالَفَ فِي الثَّلَاثَةِ لَمْ تَبْطُلْ صَلَاتُهُ. وَالِاسْتِنَادُ الَّذِي تَبْطُلُ بِهِ صَلَاةُ الْقَادِرِ عَلَى تَرْكِهِ هُوَ الَّذِي يَسْقُطُ بِسُقُوطِهِ، وَإِنْ كَانَ لَا يَسْقُطُ بِسُقُوطِهِ فَهُوَ مَكْرُوهٌ. وَأَمَّا النَّافِلَةُ فَيَجُوزُ لِلْقَادِرِ عَلَى الْقِيَامِ أَنْ يُصَلِّيَهَا جَالِسًا، وَلَهُ نِصْفُ أَجْرِ الْقَائِمِ. وَيَجُوزُ أَنْ يَدْخُلَهَا جَالِسًا وَيَقُومَ بَعْدَ ذَلِكَ أَوْ يَدْخُلَهَا قَائِمًا وَيَجْلِسَ بَعْدَ ذَلِكَ إِلَّا أَنْ يَدْخُلَهَا بِنِيَّةِ الْقِيَامِ فِيهَا فَيَمْتَنِعَ جُلُوسُهُ بَعْدَ ذَلِكَ.

 

Ẹ̀kọ́ Nípa Àwọn Ìsesí tí A Lè Gbà Kí Ìrun


Isèsí méje ni ìrun ọ̀ranyàn lè gbà jẹ́ kíkí; Mẹ́rin nínú wọn jẹ́ ọ̀ranyàn, nígbà tí mẹ́ta yókù sì jẹ́ oun tí a fẹ́. Àwọn ni ìwọ̀nyí ní sísẹ̀ n tẹ̀lé:

Àkọ́kọ́: kíkí ìrun ní ídùró láì kò fara ti ǹkankan.

Ìkejì: kíkí ìrun ní ídúró pẹ̀lú ìfara ti ǹkan.

Ìkẹta: kíkí ìrun ní ìjòkó láì kò fara ti ǹkan.

Ìkẹrin: kíkí ìrun ní ìjòkó pẹ̀lú fifi ara ti ǹkan.

Títo àwọn ọ̀nà mẹ́ẹ́rẹ̀rin yí tẹ̀lé ara wọn jẹ́ ọ̀ranyàn, ẹni tí ó bá lágbára àkọ́kọ́ nínú wọn tí ó wáá fò sórí èyí tí ó tẹ̀le, ìrun rẹ̀ ti bàjẹ́.

Ẹò wáá rí àwọn ìsesí mẹ̀ta tí èèyàn lè gbà kírun bí ó bá se fẹ́ ni ìwọ̀n yí:

Àkọ́kọ́: Kí aláìlágbára àwọn ọ̀nà mẹ́ẹ́rẹ̀rin tí ó siwájú yẹn fi ìhà ọ̀tún rẹ̀ lélẹ̀ kí ìrun.

Ìkejì: kíkí ìrun pẹ̀lú fífi ìhà àlááfíà (Òsì) lélẹ̀.

Ìkẹta: kíkí ìrun pẹ̀lú fifi ẹ̀yìn lélẹ̀.

Tí aláìlágbára àwọn ọ̀nà mẹ́ẹ́rẹ̀rin tí ó siwájú yẹn bá wáá kí ìrun pẹ̀lú èyíkéyí nínú àwọn ìsesí mẹ́ta tí ó gbẹ̀yìn yìí bí ó se wùú, ìrun rẹ̀ ní àlááfíà, kò sì bàjẹ́.

 

Àkíyèsí:

Ìfaratì tí ó lè ba ìrun ẹni tí ó lágbára láti dúró láì kò fi ara ti ǹkankan jẹ́ ni ìfaratì tí ó lágbára debi tí ó se wípé tí oun tí ó bá fi ara tì bá subú, òhun náà yóò subú tẹ̀le. Sùgbọ́n tí ìfaratì náà kò bá lágbára tó bẹ́ẹ̀, ìrun kò bàjẹ́, sùgbọ́n oun ẹ̀kọ̀ ni.

    Tí ó bá wáá jẹ́ ìrun àkígbọrẹ (Nááfílà) ni, ẹni tí ó lágbára láti dúró láì kò fi ara ti ǹkankan lè kí i ní ìjòkó, sùgbọ́n ìlàjì láádá (Ẹ̀san) ni yóó gbà. Ìgbàláyè sì wà fún un kí ó bẹ̀rẹ̀ ìrun àkígbọrẹ (Naafila) pẹ̀lú ìjòkó, kí ó parí rẹ̀ pẹ̀lú ìnàró. Tàbí kí ó bẹ̀rẹ̀ rẹ̀ pẹ̀lú ìnàró, kí ó sì parí rẹ̀ pẹ̀lú ìjòkó. Àyàfi tí ó bá jẹ́ wípé àníyàn ìnàró ni ó dà fi bẹ̀rẹ̀ ìrun naafila, èèwọ̀ ni kí ó joko parí rẹ.

Wednesday, 10 June 2020

ÌTUMỌ̀ TÍRÀ ÁHLÀRÍ (Ẹ̀kọ́ Kẹjọ)

فَصْلٌ فِي الخُشُوعِ فِي الصَّلاةِ


لِلصَّلَاةِ نُورٌ عَظِيمٌ تُشْرِقُ بِهِ قُلُوبُ الْمُصَلِّينَ، وَلَا يَنَالُهُ إِلَّا الْخَاشِعُونَ، فَإِذَا أَتَيْتَ إِلَى الصَّلَاةِ فَفَرِّغْ قَلْبَكَ مِنْ الدُّنْيَا وَمَا فِيهَا، وَاشْتَغِلَ بِمُرَاقَبَةِ مَوْلَاكَ الَّذِي تُصَلِّى لِوَجْهِهِ. وَاعْتَقِدْ أَنَّ الصَّلَاةَ خُشُوعٌ وَتَوَاضُعٌ لِلَّهِ سُبْحَانَهُ بِالْقِيَامِ وَالرُّكُوعِ وَالسُّجُودِ وَإِجْلَالٌ وَتَعْظِيمٌ لَهُ بِالتَّكْبِيرِ وَالتَّسْبِيحِ وَالذِّكْرِ. فَحَافِظَ عَلَى صَلَاتِكَ فَإِنَّهَا أَعْظَمُ الْعِبَادَاتِ، وَلَا تَتْرُكِ الشَّيْطَانَ يَلْعَبُ بِقَلْبِكَ وَيَشْغَلُكَ عَنْ صَلَاتِكَ حَتَّى يَطْمِسَ قَلْبَكَ وَيَحْرِمَكَ مِنْ لَذَّةِ أَنْوَارِ الصَّلَاةِ، فَعَلَيْكَ بِدَوَامِ الْخُشُوعِ فِيهَا فَإِنَّهَا تَنْهَى عَنْ الْفَحْشَاءِ وَالْمُنْكَرِ بِسَبَبِ الْخُشُوعِ فِيهَا، فَاسْتَعِنْ بِاللَّهِ إِنَّهُ خَيْرُ مُسْتَعَانٍ.

 

Ẹ̀kọ́ Míràn Lórí Ìfọkàn-Sìn Ọlọ́hun


Ìmọ́lẹ̀ ńlá kan ń bẹ níbi ìrun kíkí, tí ó má ń tan ìmọ́lẹ̀ sí ọkàn àwọn olùkirun. Àwọn olùfọkàn sin Ọlọ́hun lórí ìrun wọn nìkan ni ọwọ́ wọn sì má ń tẹ ìmọ́lẹ̀ náà.


Torínáà, tí o bá ti fẹ́ẹ́ kírun, pa ọkàn rẹ lófo kúrò níbi ayé àti yòdòyindin rẹ̀, kí o sì pa ọkàn rẹ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́hun tí ò ń torí rẹ̀ jọ́sìn. Sì ní àdìsọ́kàn wípé òpó ńlá tí ó gbé ìrun dùró náà ni; ìpáyá àti ìtẹríba fún Ọlọ́hun; pẹ̀lú ìdúró, ìtẹ̀ kọkọrọ (RukË‘), àti ìforíbalẹ̀ (SujËd). Àti ìbàbàrà Ọlọ́hun; pẹ̀lú síse gbólóhùn ‘Allahu Akbaru’, síse àfọ̀mọ́ (SubÍÉnallÉh), àti ìrántí Rẹ̀ (Al-Dhikr).


Sì se àmójútó ìrun rẹ, torípé ìjọsìn tí ó kàǹkà ni. Má se gba èsù láyè láti fi ọpọlọ rẹ seré tàbí darí ọkàn ìrẹ kúrò níbi ìrun kiki; kí ó lè gba ọpọlọ rẹ àti láti kọ dí rírí adùn àwọn ìmọ́lẹ̀ tí ń bẹ níbi ìrun kíkí fún ìrẹ.


Ó sì di ọ̀ranyàn fún ọ kí o dún ní mọ́ ìfọkàn-sin Ọlọ́hun, nítorípé yóò maa darí ìrẹ kúrò níbi ìwà ìbàjẹ́ àti ìwà èérí. Wá ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́hun lórí fífi ìfọkàn-sin Ín rọ ìrẹ lọ́rùn, torípé Òun (Ọlọ́hun) nìkan ni ó lè fi rọ ènìyàn lọ́rùn.


Monday, 8 June 2020

ÌTUMỌ̀ TÍRÀ ÁHLÀRÍ (Ẹ̀kọ́ Keje)

فَضَائِلُ الصَّلَاةِ وَمَكرُوهاتُها
Àwọn Oun tí Wọ́n Fẹ́ Sìse Wọ́n àti Àwọn Èyí tí Wọ́n Kọ̀ Nibi Ìrun Kíkí


صورة الأخضري.jpg
(وَفَضَائِلُهَا) رَفْعُ الْيَدَيْنِ عِنْدَ الْإِحْرَامِ حَتَّى تُقَابِلَا الْأُذُنَيْنِ وَقَوْلُ الْمَأْمُومِ وَالْفَذِّ: رَبَّنَا وَلَكَ الْحَمْدُ، وَالتَّأْمِينُ بَعْدَ الْفَاتِحَةِ لِلْفَذِّ وَالْمَأْمُومِ، وَلَا يَقُولُهَا الْإِمَامُ إِلَّا فِي قِرَاءَةِ السِّرِّ، وَالتَّسْبِيحُ فِي الرُّكُوعِ وَالدُّعَاءُ فِي السُّجُودِ، وَتَطْوِيلُ الْقِرَاءَةِ فِي الصُّبْحِ وَالظُّهْرِ تَلِيهَا وَتَقْصِيرُهَا فِي الْعَصْرِ وَالْمَغْرِبِ، وَتَوَسُّطُهَا فِي الْعِشَاءِ، وَتَكُونُ السُّورَةُ الْأُولَى قَبْلَ الثَّانِيَةِ وَأَطْوَلَ مِنْهَا، وَالْهَيْئَةُ الْمَعْلُومَةُ فِي الرُّكُوعِ وَالسُّجُودِ وَالْجُلُوسِ وَالْقُنُوتِ سِرًّا قَبْلَ الرُّكُوعِ وَبَعْدَ السُّورَةِ فِي ثَانِيَةِ الصُّبْحِ وَيَجُوزُ بَعْدَ الرُّكوعِ وَالدُّعَاءُ بَعْدَ التَّشَهُّدِ الثَّانِي، وَيَكُونُ التَّشَهُّدُ الثَّانِي أَطْوَلَ مِنَ الْأَوَّلِ وَالْتَّيَامُنُ بِالسَّلَامِ وَتَحْرِيكُ السَّبَّابَةِ فِي التَّشَهُّدِ.


Àwọn oun tí wọ́n fẹ́ síse wọn níbi ìrun kiki ni: (1) Gbígbé ọwọ́ sókè titi yóò fi kan etí níbi síse kábárà (Allahu Akbar) alákọ́kọ́. (2) Wíwí gbólóhùn ‘Rabbanaa walakal hamdu’fún ẹni tí ń tẹ̀lé ìmáámù àti ẹni tí ó ń dá ìrun kí. (3) Wíwí gbólóhùn ‘Aamiina’ lẹ́yìn kika ‘Suratul Faatihah’ fún ẹni tí ó ń tẹ̀lé ìmáámù àti ẹni tí ó ń dá ìrun kí, ìmáámù kò sì níí wí i àyàfi níbi ìkéwú jẹ́ẹ́jẹ́. (4) Síse gbólóhùn àfọ̀mọ́ ‘Subhaanallahi’ ní ìtẹríba (Rukuu). (5) Àdúà síse ní ìforíbalẹ̀ (Sujuudu). (6) Ìkéwú tí ó jagun níbi ìrun àsùnbáà (Subui), àti àílà (Duhri). (7) Ìkéwú mọ ní ìwọ̀nba níbi ìrun àlásàrì (Asri), àti Mọ́gáríbì (Magribi). (8) Ìkéwú ní ìwọ̀ntunwọ̀nsí níbi ìrun ishai. (9) Kí kéwú ọ̀pá alákọ́kọ́ jagun ju ti ọ̀pá ẹlẹ́kejì lọ. (10) Àwọn ìṣesí bí ó se yẹ kí ó rí ní ìtẹríba (Rukuu) bíi títẹ́ ẹ̀yìn pẹrẹsẹ, ìforí kanlẹ̀ (Sujuudu) bíi dída àtẹlẹwọ́ délẹ̀, àti ìjòkó (Juluusu) títẹ́ ẹsẹ̀ méjéèjì sílẹ̀ láti jókó lé e. (11) Kíké adua ‘Kunuutu’ ní jẹ́ẹ́jẹ́ síwájú ìtẹríba (Rukuu) lẹ́yìn kéwú ní ọ̀pá keji ìrun àsúnbà (Subhi). Kò sì buru kí ó jẹ́ síse lẹ́yìn ìtẹríba (Rukuu) náà. (12) Àdúà síse lẹ́yìn ‘Àtááyá’ ìkẹyìn. (13) Fífa ‘Àtááyá’ ìkẹyìn gùn ju ti alákọ́kọ́ lọ. (14) Yíyí orí níbi gbolohun sálámọ̀. (15) Mími ọmọníka ìfábẹ̀lá níbi ‘Àtááyá’.

وَيُكْرَهُ الِالْتِفَاتُ فِي الصَّلَاةِ، وَتَغْمِيضُ الْعَيْنَيْنِ، وَالْبَسْمَلَةُ وَالتَّعَوُّذُ فِي الْفَرِيضَةِ وَيَجُوزَانِ فِي النَّفْلِ، وَالْوُقُوفُ عَلَى رِجْلٍ وَاحِدَةٍ إِلَّا أَنْ يَطُولَ قِيَامُهُ، وَاقْتِرَانُ رِجْلَيْهِ وَجَعْلُ دِرْهَمٍ أَوْ غَيْرِهِ فِي فَمِهِ، وَكَذَلِكَ كُلُّ مَا يُشَوِّشُهُ فِي جَيْبِهِ أَوْ كُمِّهُ أَوْ عَلَى ظَهْرِهِ، وَالتَّفَكُّرُ فِي أُمُورِ الدُّنْيَا، وَكُلُّ مَا يَشْغُلْهُ عَنِ الْخُشُوعِ فِي الصَّلَاةِ.

Wọ́n kọ: (1) Wíwo ìhín wo ọ̀hún lórí ìrun. (2) Dídi ojú. (3) Kíké ‘Bismillahi’ pẹ̀lú ‘Auudu billahi’ níbi ìrun ọ̀ranyàn, kò sì burú níbi àkígbọrẹ (Naafila). (4) Ìdúró lórí ẹsẹ̀ kan (Kátò) fi kírun, áyàfi tí ó bá bùkáátà sí i, latari jíjágùn ìdúró. (5) Lílọ́ ẹsẹ̀ méjéèjì pọ̀ lórí ìrun. (6) Fífi ǹkan (bíi owó dirhamu àti àfijọ rẹ̀) tí ó le dí kíka kéwú dáadáa sẹ́nu lórí ìrun. Bẹ́ẹ̀ náà ni kíkó gbogbo oun tí ó lè se ìdíwọ́ sí àpò asọ, ọwọ́ rẹ̀, àti ara rẹ̀. (7) Ìmaa ronú yòdòyindin ayé lórí ìrun, àti gbogbo oun tí ó lè se ìdíwọ́ fún ìfarabalẹ̀ lórí ìrun.

The timeless lessons from Abū Bakr’s companionship with the Prophet ﷺ during the migration to Madinah

  كِتَابُ فَضَائِلِ الصَّحَابَةِ مَنَاقِبُ أَبِي بَكْرٍ رَضِي عَنْهُ بَابُ قَوْلِهِ تَعَالَى: ﴿إِذْ يَقُولُ لِصَاحِبِهِ لَا تَحْزَنْ إِنَّ ا...