Wednesday, 10 June 2020

ÌTUMỌ̀ TÍRÀ ÁHLÀRÍ (Ẹ̀kọ́ Kẹjọ)

فَصْلٌ فِي الخُشُوعِ فِي الصَّلاةِ


لِلصَّلَاةِ نُورٌ عَظِيمٌ تُشْرِقُ بِهِ قُلُوبُ الْمُصَلِّينَ، وَلَا يَنَالُهُ إِلَّا الْخَاشِعُونَ، فَإِذَا أَتَيْتَ إِلَى الصَّلَاةِ فَفَرِّغْ قَلْبَكَ مِنْ الدُّنْيَا وَمَا فِيهَا، وَاشْتَغِلَ بِمُرَاقَبَةِ مَوْلَاكَ الَّذِي تُصَلِّى لِوَجْهِهِ. وَاعْتَقِدْ أَنَّ الصَّلَاةَ خُشُوعٌ وَتَوَاضُعٌ لِلَّهِ سُبْحَانَهُ بِالْقِيَامِ وَالرُّكُوعِ وَالسُّجُودِ وَإِجْلَالٌ وَتَعْظِيمٌ لَهُ بِالتَّكْبِيرِ وَالتَّسْبِيحِ وَالذِّكْرِ. فَحَافِظَ عَلَى صَلَاتِكَ فَإِنَّهَا أَعْظَمُ الْعِبَادَاتِ، وَلَا تَتْرُكِ الشَّيْطَانَ يَلْعَبُ بِقَلْبِكَ وَيَشْغَلُكَ عَنْ صَلَاتِكَ حَتَّى يَطْمِسَ قَلْبَكَ وَيَحْرِمَكَ مِنْ لَذَّةِ أَنْوَارِ الصَّلَاةِ، فَعَلَيْكَ بِدَوَامِ الْخُشُوعِ فِيهَا فَإِنَّهَا تَنْهَى عَنْ الْفَحْشَاءِ وَالْمُنْكَرِ بِسَبَبِ الْخُشُوعِ فِيهَا، فَاسْتَعِنْ بِاللَّهِ إِنَّهُ خَيْرُ مُسْتَعَانٍ.

 

Ẹ̀kọ́ Míràn Lórí Ìfọkàn-Sìn Ọlọ́hun


Ìmọ́lẹ̀ ńlá kan ń bẹ níbi ìrun kíkí, tí ó má ń tan ìmọ́lẹ̀ sí ọkàn àwọn olùkirun. Àwọn olùfọkàn sin Ọlọ́hun lórí ìrun wọn nìkan ni ọwọ́ wọn sì má ń tẹ ìmọ́lẹ̀ náà.


Torínáà, tí o bá ti fẹ́ẹ́ kírun, pa ọkàn rẹ lófo kúrò níbi ayé àti yòdòyindin rẹ̀, kí o sì pa ọkàn rẹ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́hun tí ò ń torí rẹ̀ jọ́sìn. Sì ní àdìsọ́kàn wípé òpó ńlá tí ó gbé ìrun dùró náà ni; ìpáyá àti ìtẹríba fún Ọlọ́hun; pẹ̀lú ìdúró, ìtẹ̀ kọkọrọ (RukË‘), àti ìforíbalẹ̀ (SujËd). Àti ìbàbàrà Ọlọ́hun; pẹ̀lú síse gbólóhùn ‘Allahu Akbaru’, síse àfọ̀mọ́ (SubÍÉnallÉh), àti ìrántí Rẹ̀ (Al-Dhikr).


Sì se àmójútó ìrun rẹ, torípé ìjọsìn tí ó kàǹkà ni. Má se gba èsù láyè láti fi ọpọlọ rẹ seré tàbí darí ọkàn ìrẹ kúrò níbi ìrun kiki; kí ó lè gba ọpọlọ rẹ àti láti kọ dí rírí adùn àwọn ìmọ́lẹ̀ tí ń bẹ níbi ìrun kíkí fún ìrẹ.


Ó sì di ọ̀ranyàn fún ọ kí o dún ní mọ́ ìfọkàn-sin Ọlọ́hun, nítorípé yóò maa darí ìrẹ kúrò níbi ìwà ìbàjẹ́ àti ìwà èérí. Wá ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́hun lórí fífi ìfọkàn-sin Ín rọ ìrẹ lọ́rùn, torípé Òun (Ọlọ́hun) nìkan ni ó lè fi rọ ènìyàn lọ́rùn.


No comments:

The timeless lessons from Abū Bakr’s companionship with the Prophet ﷺ during the migration to Madinah

  كِتَابُ فَضَائِلِ الصَّحَابَةِ مَنَاقِبُ أَبِي بَكْرٍ رَضِي عَنْهُ بَابُ قَوْلِهِ تَعَالَى: ﴿إِذْ يَقُولُ لِصَاحِبِهِ لَا تَحْزَنْ إِنَّ ا...