Sunday, 29 October 2017

ÌTUMỌ̀ TÍRÀ ÁHLÀRÍ (Ẹ̀kọ́ Kẹfà)

فَصْلٌ فِي الْأَوْقَاتِ
ÌPÍN TÍ Ó Ń SÀLÀYÉ ÀWỌN ÀKÓKÒ ÌRUN
اَلْوَقْتُ الْمُخْتَارُ لِلظُّهْرِ مِنْ زَوَالِ الشَّمْسِ إِلَى آخَرَ الْقَامَةِ. وَالْمُخْتَارُ لِلْعَصْرِ مِنْ الْقَامَةِ إِلَى الِاصْفِرَارِ وَضَرُورِيُّهُمَا إِلَى الْغُرُوبِ. وَالْمُخْتَارُ لِلْمَغْرِبِ: قَدْرُ مَا تُصَلَّى فِيهِ بَعْدَ شُرُوطِهَا. وَالْمُخْتَارُ لِلْعَشَاءِ مِنْ مَغِيبِ الشَّفَقِ إِلَى ثُلُثِ اللَّيْلِ الْأَوَّلِ. وَضَرُورِيُّهُمَا إِلَى طُلُوعِ اَلْفَجْرِ. وَالْمُخْتَارُ لِلصُّبْحِ مِنَ الْفَجْرِ إِلَى الْإِسْفَارِ الْأَعْلَى وَضَرُورِيُّهُ إِلَى طُلُوعِ الشَّمْسِ، وَالْقَضَاءُ فِي الْجَمِيعِ مَا وَرَاءَ ذَلِكَ.

Ojúlówó àkókò tí wọ́n sà ní ẹ̀sà fún ìrun Àílà (Zuhr) ní ìgbà tí òòrùn bá yẹ àtààrí parí sí ìgbà tí ìnàró gbogbo ǹkan yóò fi se déédé ara wọn. Àkókò ẹ̀sà fún ìrun Àláásàrì (Asr), àti àsìkò làlúrí fún ìrun àílà (Dhuhr) ni ìgbà tí ìnàró gbogbo ǹkan bá se déédé ara wọn títí ojú ọjọ́ yóò fi di òfééfèé (Yẹ́lò). Nígbà tí àsìkò làlúrí fún ìrun Àílà (Dhuhr) àti àsìkò ẹ̀sà fún àláásàrì (Asr) bẹ̀rẹ̀ láti ìgbà tí ojú ọjọ́ bá ti di òfééfèé (Yẹ́lò) títí òòrùn yóò fi wọ̀. Àkókò ẹ̀sà fún ìrun Mọ́gáríbì (Magrib) ni òdiwọ̀n ìgbà tí ìrun náà yóò fi jẹ́ kíkí lẹ́yìn tí gbogbo májẹ̀mu ti ó gbe dúró ti pé lẹ́yìn tí òòrùn ti wọ̀. Àkókò ẹ̀sà fún ìrun Ìsháì (Ishai) ni ìgbà tí awòǹpàpà (Tanmọóko) yóò fi wọlé títí di ídá mẹ́ta àkọ́kọ́ nínú òru. Àsìkò làlúrí fún ìrun Ìsháì sì wà títí di àsìkò lílà àlùfájàrí. Àsìkò ẹ̀sà fún ìrun Àsùnbáà (Subhi) ni ìgbà tí àlùfájàrí bá ti là títí di ìgbà tí òye yóó fi mọ́lẹ̀ kedere. Àsìkò làlúrí rẹ̀ sì lọ títí di ìgbà tí òòrùn yóò fi yọ. Ìrun tí ó bá sì ti bọ́ sí ẹ̀yìn àwọn àsìkò làlúrí ti bọ́ sí ipò gbèsè sísan.

وَمَنْ أَخَّرَ الصَّلَاةَ حَتَّى خَرَجَ وَقْتُهَا فَعَلَيْهِ ذَنْبٌ عَظِيمٌ إِلَّا أَنْ يَكُونَ نَاسِيًا أَوْ نَائِمًا. وَلَا تُصَلَّى نَافِلَةٌ بَعْدَ صَلَاةِ الصُّبْحِ إِلَى ارْتِفَاعِ الشَّمْسِ، وَبَعْدَ صَلَاةِ الْعَصْرِ إِلَى صَلَاةِ الْمَغْرِبِ، وَبَعْدَ طُلُوعِ الْفَجْرِ إِلَّا الْوِرْدَ لِنَائِمٍ عَنْهُ وَعِنْدَ جُلُوسِ إِمَامِ الْجُمُعَةِ عَلَى الْمِنْبَرِ، وَبَعْدَ الْجُمْعَةِ حَتَّى يَخْرُجَ مِنَ الْمَسْجِدِ.

Ẹni tí ó bá lọ́ ìrun lára tí àsìkò rẹ̀ fi kọjá, ẹrù ẹ̀sẹ̀ ńlá ń bẹ lórí rẹ̀, àyàfi tí ó bá gbàgbé tàbí ó sùn lọ. Kò sì sí ìgbàláyè fún àkígbọrẹ (Nafila) lẹ́yìn ìrun Àsùnbáà (Subhi) títí tí òòrùn yóò fi kan àtààrí. Bẹ́ẹ̀ni kó sí fún un lẹ́yìn ìrun Àláásàrì (Asr) títí di àsìkò Mọ́gáríbì (Magrib). Kò sì sí fún un lẹ́yìn tí Àlùfájàrí (Fajr) bá ti là, àyàfi Nafila tí ó sùn gbàgbé láti se. Kò tún sí fún un lẹ́yìn tí ìmámù bá ti gun pẹpẹ (Minbari) ní ọjọ́ Jímọ̀, àti lẹ́yìn ìrun Jímọ̀ títí tí yóò fi jáde ní Mọ́sálásí.

فَصْلٌ فِي شُرُوطِ الصَّلَاةِ
ÌPÍN TÍ Ó Ń SÀLÀYÉ ÀWỌN MÁJẸ̀MÚ ÌRUN

وَشُرُوطُ الصَّلَاةِ طَهَارَةُ الْحَدَثِ وَطَهَارَةُ الْخَبَثِ مِنَ الْبَدَنِ وَالثَّوْبِ وَالْمَكَانِ وَسَتْرُ الْعَوْرَةِ وَاسْتِقْبَالُ الْقِبْلَةِ، وَتَرْكُ الْكَلَامِ وَتَرْكُ الْأَفْعَالِ الْكَثِيرَةِ. وَعَوْرَةُ الرَّجُلِ مَا بَيْنَ السُّرَّةِ وَالرُّكْبَةِ، وَالْمَرْأَةُ كُلُّهَا عَوْرَةٌ مَا عَدَا الْوَجْهَ وَالْكَفَّيْنِ. وَتُكْرَهُ الصَّلَاةُ فِي السَّرَاوِيلِ، إِلَّا إِذَا كَانَ فَوْقَهَا شَيْءٌ. وَمَنْ تَنَجَّسِ ثَوْبُهُ وَلَمْ يَجِدْ ثَوْبًا غَيْرَهُ وَلَمْ يَجِدْ مَاءً يَغْسِلُهُ بِهِ أَوْ لَمْ يَكُنْ عِنْدَهُ مَا يَلْبَسُ حَتَّى يَغْسِلَهُ وَخَافَ خُرُوجَ الْوَقْتِ صَلَّى بِنَجَاسَتِهِ. وَلَا يَحِلُّ تَأْخِيرُ الصَّلَاةِ لِعَدَمِ اَلطَّهَارَةِ، وَمَنْ فَعَلَ ذَلِكَ فَقَدْ عَصَى رَبَّهُ. وَمَنْ لَمْ يَجِدْ مَا يَسْتُرُ بِهِ عَوْرَتَهُ صَلَّى عُرْيَانًا. وَمَنْ أَخْطَأَ الْقِبْلَةَ أَعَادَ فِي الْوَقْتِ، وَكُلُّ إِعَادَةٍ فِي الْوَقْتِ فَهِيَ فَضِيلَةٌ. وَكُلُّ مَا تُعَادُ مِنْهُ الصَّلَاةُ فِي الْوَقْتِ فَلَا تُعَادُ مِنْهُ الْفَائِتَةُ وَالنَّافِلَةُ.

Àwọn májẹ̀mú ni: (1) Ìmọra níbi ẹ̀gbin. (2) Ìmú ẹ̀gbin kúrò ní ara, asọ, àti ààyè ìkírun. (3) Bíbo ìhòòhò. (4) Dídojúkọ kàábà. (5) Gbígbé ọ̀rọ̀ sísọ (Tí ó bá yàtọ̀ sí oun tí a fí ń se ìjọsìn ìrun) jù sílẹ̀. (6) Gbígbé isẹ́ ọlọ́pọ̀lọpọ̀ (Tí ó bá yàtọ̀ sí àwọn tí a fí ń se ìjọsìn ìrun) jù sílẹ̀.  Ìhòòhò ọkùnrin lórí ìrun ni àlàfo ìdajì ara (Ìdodo) títí dé orúnkún rẹ̀. Ìhòòhò obìnrin sì ni gbogbo ara rẹ̀ pátá tí a bá yọwọ́ ojú àti àtẹlẹwọ́ rẹ̀ méjéèjì. Wọ́n sì kọ kíkí ìrun pẹ̀lu sòkòtò lásán láì kò wọ ǹkan sí òkè rẹ̀. Ẹni tí ẹ̀gbin bá wà ní ara asọ rẹ̀, tí ó sàfẹ́kù asọ míràn, tí kò sì rí omi tí ó lè fi mọ́ ọn, tàbí kò ní asọ òmíràn tí ó le fi sọ́rùn láti fi se ìmọ́tótó èyí tí ẹ̀gbin ńbẹ lára rẹ̀, tí ó sì ń bẹ̀rù kí àsìkò ìrun má jáde mọ́ ọn lọ́wọ́, Ó lè kírun pẹ̀lú ẹ̀gbin tí ó wà lára asọ rẹ̀.  Lílọ́ ìrun lára kò tọ́ ní tìtorí àìmọ́ra, ẹni tí ó bá fi ìrun lọ́ra nítorí ìdí yí ti dá ẹ̀sẹ̀ sí Ọlọ́hun ọba rẹ̀.  Ẹni tí ó bá sì se àfẹ́kù oun tí ó lè fi bo ìhòòhò rẹ̀, yóò kí ìrun rẹ̀ ní ìhòòhò náà ni. Ẹni tí ó bá sì se àsìyàn ibùdojúkọ kírun (Kibla) yóò tun kí lópin ìgbà tí àsìkò ìrun náà kò bá tíì jáde. Gbogbo ààyè tí wọ́n bá ti fẹ́ sísan ìrun padà lópin ìgbà tí àsìkò ìrun kò bá tíì jáde ń dá lórí wípé “Ọlá ńbẹ níbi síse é”, “Bí ènìyàn kò bá sì sé, kò buru”. Gbogbo ìse tí ó bá sì bèèrè fún sísan ìrun padà lópin ìgbà tí àsìkò rẹ̀ kò bá tíì jáde, èyí tí ó bá ti jáde àti àkígbọrẹ (Naafila) kò níí jẹ́ sísan padà nítorí wọn.

فَصْلٌ: فَرَائِضُ الصَّلَاةِ: نِيَّةُ الصَّلَاةِ الْمُعَيَّنَةِ، وَتَكْبِيرَةُ الْإِحْرَامِ وَالْقِيَامُ لَهَا، وَالْفَاتِحَةُ وَالْقِيَامُ لَهَا، وَالرُّكُوعُ وَالرَّفْعُ مِنْهُ، وَالسُّجُودُ عَلَى الْجَبْهَةِ وَالرَّفْعُ مِنْهُ، وَالِاعْتِدَالُ، وَالطُّمَانِينَةُ، وَالتَّرْتِيبُ بَيْنَ فَرَائِضِهَا، وَالسَّلَامُ وَجُلُوسُهُ الَّذِي يُقَارِنُهُ.

Ẹ̀kọ́ Míràn- Àwọn Ọ̀ranyàn Ìrun ni: (1) Mímú àníyàn irú ìrun tí a fẹ́ẹ́ kí gan gan wá. (2) Gbígbé kábárá (Allahu Akbar tí a fí ń sọ gbogbo ìse àti ọ̀rọ̀ míràn tí ó yàtọ̀ sí èyí tí a fi ń se ìjọsìn ìrun di èèwọ̀). (3) Dìdúró gbé kábárá. (4) Kíka ọgbà ọ̀rọ̀ ìsí Alukuraani (Suratul Faatiha). (5) Dìdúró ka ọgbà ọ̀rọ̀ ìsí Alukuraani (Suratul Faatiha). (6) Títẹríba (Rukuu). (7) Sísí orí kúrò ní ítẹríba (Rukuu). (8) Fífi iwájú orí kanlẹ̀ (Sujuudu). (9) Gbígbé orí nílẹ̀. (10) Dídúró dáradára lẹ́yìn ísí orí kúrò ní ítẹríba (Rukuu), àti ìjókó dáradára lẹ́yìn gbígbé orí nílẹ̀. (11) Fífara balẹ̀ níbi ìdúró àti ìjòkó. (12) Tító àwọn ọ̀ranyàn ìrun yí tẹ̀lé ara wọn. (13) Píparí ìrun pẹ̀lú sálámọ̀. (14) Jíjòkó sálámọ̀.

(وَشَرْطُ) النِّيَّةِ مُقَارَنَتُهَا لِتَكْبِيرَةِ الْإِحْرَامِ.

Májẹ̀mu àníyàn ni síse é mọ́ kábárá (Allahu Akbar tí a fí ń sọ gbogbo ìse àti ọ̀rọ̀ míràn tí ó yàtọ̀ sí èyí tí a fi ń se ìjọsìn ìrun di èèwọ̀).

(وَسُنَّتُهَا): الْإِقَامَةُ، وَالسُّورَةُ الَّتِي بَعْدَ الْفَاتِحَةِ، وَالْقِيَامُ لَهَا، وَالسِّرُّ فِيمَا يُسَرُّ فِيهِ، وَالْجَهْرُ فِيمَا يُجْهَرُ فِيهِ، وَسَمِعَ اللَّهُ لِمَنْ حَمِدَهُ. وَكُلُّ تَكْبِيرَةٍ سُنَّةٌ إِلَّا الْأُولَى وَالتَّشَهُّدَانِ وَالْجُلُوسُ لَهُمَا، وَتَقْدِيمُ الْفَاتِحَةِ عَلَى السُّورَةِ وَالْتَّسْلِيمِةُ الثَّانِيَةُ وَالثَّالِثَةُ لِلْمَأْمُومِ، وَالْجَهْرُ بَالتَّسْلِيمِةِ الْوَاجِبَةِ، وَالصَّلَاةُ عَلَى رَسُولِ اللَّهِ صَلَّى اللَّهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ، وَالسُّجُودُ عَلَى الْأَنْفِ وَالْكَفَّيْنِ وَالرُّكْبَتَيْنِ وَأَطْرَافِ الْقَدَمَيْنِ وَالسُّتْرَةُ لِغَيْرِ الْمَأْمُومِ وَأَقَلُّهَا غِلَظُ رُمْحٍ وَطُولُ ذِرَاعٍ طَاهِرٍ ثَابِتٍ غَيْرِ مُشَوَّشٍ.


Ìlànà Ànábì Lórí Ìrun Kíkí ni: (1) Gbígbé ìrun dúró (Ìkáámà). (2) Kíka ọgbà ọ̀rọ̀ (Suura) míràn lẹ́yín ọgbà ọ̀rọ̀ ìsí Alukuraani (Suratul Faatiha). (3) Dídúró ka ọgbà ọ̀rọ̀ (Suura) míràn. (4) Kíka kéwú jẹ́ẹ́jẹ́ láàyè rẹ̀. (5) Kíka kéwú sókè láàyè rẹ̀. (6) Wíwí gbólóhùn “Semial lahu liman hamdau” níbi sísí orí kúrò ní ítẹríba (Rukuu). (7) Gbogbo kábárà tí ó bá ti yàtọ̀ sí kábárà ìbẹ̀rẹ̀ ìrun. (8) Síse àtááyá méjéèjì. (9) Jíjòkó se àtááyá méjéèjì. (10) Kíka ọgbà ọ̀rọ̀ ìsí Alukuraani (Suratul Faatiha) síwájú ọgbà ọ̀rọ̀ (Suura) míràn. (11) Síse sálámọ̀ kejì àti ìkẹta fún olùtẹ̀lé ìmáámù ní ìparí ìrun. (12) Gbígbé òhùn sókè se sálámọ̀ àkọ́kọ́ tí ó jẹ́ ọ̀ranyàn. (13) Síse ìtọrọ ìkẹ́ àti ìgẹ̀ fún Ànábì (Àsàláátù) níbi àtááyá ìkángun ìrun. (14) Fífi imú, àtẹlẹwọ́ méjéèjì, orúnkún méjéèjì, àwọn ọmọníka ẹsẹ̀ méjéèjì lẹ́lẹ̀ níbi ìforí kanlẹ̀. (15) Lílo agàgá fún ìmáámù. Agàgá yí kéré jù aò rí irú rẹ̀ rí ni kí ó nípọn bí ọ̀kọ̀, kí ó sì gùn ní òdiwọ̀n ìgbùnwọ́ kan tí ó mọ́, tí ó le dúró sinsin, tí kò sì níí jẹ́ oun ìdíwọ́ fún olùkírun.

Thursday, 26 October 2017

ÌTUMỌ̀ TÍRÀ ÁHLÀRÍ (Ẹ̀kọ́ Karùn)

فَصْلٌ فِي الْحَيْضِ
ÌPÍN TÍ Ó Ń SÀLÀYÉ ǸKAN OSÙ OBÌNRIN (ÉÉLÀ)

وَالنِّسَاءُ مُبْتَدَأَةٌ وَمُعْتَادَةٌ وَحَامِلٌ، وَأَكْثَرُ الْحَيْضِ لَلْمُبْتَدِأَةِ خَمْسَةَ عَشَرَ يَوْمًا. وَلِلْمُعْتَادَةِ عَادَتُهَا. فَإِنْ تَمَادَى بِهَا الدَّمُ زَادَتْ ثَلَاثَةَ أَيَّامٍ مَا لَمْ تُجَاوِزْ خَمْسَةَ عَشَرَ يَوْمًا. وَلِلْحَامِلِ بَعْدَ ثَلَاثَةِ أَشْهُر خَمْسَةَ عَشَرَ يَوْمًا وَنَحْوُهَا، وَبَعْدَ سِتَّةِ أَشْهُرٍ عِشْرُونَ وَنَحْوُهَا، فَإِنْ تَقَطَّعَ الدَّمُ لَفَّقَتْ أَيَّامَهُ حَتَّى تُكَمِّلَ عَادَتَهَا. وَلَا يَحِلُّ لِلْحَائِضِ صَلَاةٌ وَلَا صَوْمٌ وَلَا طَوَافٌ وَلَا مَسُّ مُصْحَفٍ وَلَا دُخُولُ مَسْجِدٍ. وَعَلَيْهَا قَضَاءُ الصَّوْمِ دُونَ الصَّلَاةِ، وَقِرَاءَتُهَا جَائِزَةٌ، وَلَا يَحِلُّ لِزَوْجِهَا فَرْجُهَا وَلَا مَا بَيْنَ سُرَّتِهَا وَرُكْبَتَيْهَا حَتَّى تَغْتَسِلَ.

Ìran obinrin níbi ǹkan osù síse lè jẹ́: (1) Olùsẹ̀sẹ̀ bẹ̀rẹ̀, (2) Ẹni tí kò sẹ̀sẹ̀ maa se ǹkan osù (Ẹni tí ǹkan osù ti di àláádà rẹ̀), (3) Àti Aboyún. Ó pọ̀jù, a kò rí irú rẹ̀ rí làti fi se ǹkan osù fún olùsẹ̀sẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni ọjọ́ mẹ́ẹ̀dógún (15). Ó sì pọ̀jù, a kò rí irú rẹ̀ rí làti fi se ǹkan osù fún ẹni tí kò sẹ̀sẹ̀ maa se ǹkan osù (Ẹni tí ǹkan osù ti di àláádà rẹ̀) ni iye ọjọ́ tí ó ti bá sáábà láti máá fi sé tẹ́lẹ̀. Tí ẹ̀jẹ̀ ǹkan osù bá wáá kọ̀ tí ó se aláìdá ní àsìkò tí ó tí ó ti bá sáábà dídá, olùse ǹkan osù yóò wo ojú rẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta si kí ó tóó di ẹ̀jẹ̀ àwọ́ọ̀dá, lópin ìgbà tí ọjọ́ ǹkan osù kò bá tíì pé ọjọ́ mẹ́ẹ̀dógún (15) tẹ́lẹ̀, tàbí kò níí lé ní ọjọ́ mẹ́ẹ̀dógún (15) nígbà tí ọjọ́ mẹ́ta bá gùn ún  (Tí ọjọ́ tí ó wà láàrin àláádà rẹ̀ sí ọjọ́ mẹ́ẹ̀dógún (15) kò bá tó mẹ́ta, iye ọjọ́ tí ó bá kù tí yóò fi pé ni yóò fi kún un, gẹ́gẹ́ bíi méjì tàbí ẹyọkan). Sùgbọ́n fún ìran aboyun, ó pọ̀jù, a kò rí irú rẹ̀ rí làti fise ǹkan osù fún un –ìyẹn tí ǹkan osù rẹ̀ bá tún ń wá lasiko tí ó diwọ́ disẹ̀ sinu- lẹ́yìn osù mẹ́ta alákọ̀kọ́, ni ọjọ́ mẹ́ẹ̀dógún (15) àti oun tí ó sún mọ́ ọn. Ó sì pọ̀jù, a kò rí irú rẹ̀ rí làti fise ǹkan osù fún un lẹ́yìn tí osù mẹ́fà ti kọjá ni ogúnjọ́ (20) àti oun tí ó sún mọ́ ọn. Tí ẹ̀jẹ̀ ǹkan osù aboyún bá wáá ń wá ségesège –bíi kó wá fún ígbà díẹ̀, kó dá fún ìgbà díẹ̀- yóò só àwọn ọjọ́ náà pọ̀ tí yóò fi pé iye ọjọ́ àláádà rẹ̀ tàbi ọjọ́ tí ó pọ̀ jùlọ tí ó yẹ kó fi sé, kí ó tóó gbe síipò àwọ́ọ̀dá. Kò tọ́ fún obinrin tí ó ń se ǹkan osù (Éélà) lọ́wọ́ kí ó kí ìrun, kí ó gba ààwẹ̀, kí ó pòòrì ilé Ọlọ́hun (Kaaba), kí ó gbá ìwé mímọ́ (Àlùkùráánì) mú, àti kí ó wọ mọ́sálásí. Ọ̀ranyàn ni fún un kí ó san ààwẹ̀ tí ó bá jẹ ní àsìkò tí ó ń se ǹkan osù (Éélà) lọ́wọ́. Kò sì níí san ìrun tí ó bá bọ́ mọ́ ọn lọ́wọ́ lasiko yí. Ìgbàláyè wà fún un láti yọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́hun (Àlùkùráánì) kà. Kò sì sí ìgbàláyè fún ẹlẹ́tọ́ (Ọkọ) rẹ̀ láti súnmọ́ níbi ojú ara rẹ̀, áti gbígbádùn pẹ̀lú ààyè tíó wà ní àlàfo ìdajì ara (Ìdodo) rẹ̀ titi dé ibi orúnkún, títí tí yóó fi mọ́ra.

فَصْلٌ فِي النِّفَاسِ
ÌPÍN TÍ Ó Ń SÀLÀYÉ Ẹ̀JẸ̀ ÌBIMỌ OBÌNRIN (NIFAASI)

وَالنِّفَاسُ كَالْحَيْضِ فِي مَنْعِهِ، وَأَكْثَرُهُ سِتُّونَ يَوْمًا. فَإِذَا انْقَطَعَ الدَّمُ قَبْلَهَا وَلَوْ فِي يَوْمِ الْوِلَادَةِ، اغْتَسَلَتْ وَصَلَّتْ. فَإِذَا عَاوَدَهَا الدَّمُ، فَإِنْ كَانَ بَيْنَهُمَا خَمْسَةَ عَشَرَ يَوْمًا فَأَكْثَرَ كَانَ الثَّانِي حَيْضًا، وَإِلَّا ضُمَّ إِلَى الْأَوَّلِ وَكَانَ مِنْ تَمَامِ اَلنِّفَاسُ.

Ẹ̀jẹ̀ ìbimọ (Nifaasi) kó yàtọ̀ sí ẹ̀jẹ̀ ǹkan osù (Éélà) níbi àwọn ǹkan tí ìgbàláyè àti èyí tí kò sì ìgbàláyè fún síse wọ́n. Ó pọ̀jù, a kò rí irú rẹ̀ rí fún obìnrin làti fi se ẹ̀jẹ̀ ìbimọ (Nifaasi)  ni ọgọ́ta ọjọ́ (60). Tí ẹ̀jẹ̀ ìbimọ bá dá síwájú ọgọ́ta ọjọ́ (60), koda kí ó jẹ́ ọjọ́ tí ọmọ waye náà ni, ẹni tí ó bímọ náa yóó wẹ̀, yóó sì máa kí ìrun. Tí ó bá tún wáá rí ẹ̀jẹ̀ míràn lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ẹ̀dógún (15) lọ sókè -lẹ́yìn tí ẹ̀jẹ̀ ìbimọ ti kọ́kọ́ dá- ipò ẹ̀jẹ̀ ǹkan osù (Éélà) ni yóó gbe sí. Tí kò bá tó ọjọ́ mẹ́ẹ̀dógún (15) tí ó fi rí ẹ̀jẹ̀ padà -lẹ́yìn tí ẹ̀jẹ̀ alákọ̀kọ́ ti dá- yóò si mọ́ ẹ̀jẹ̀ ìbimọ (Nifaasi), tí yóò maa jẹ́ ìparí rẹ̀.

Friday, 20 October 2017

ÌTUMỌ̀ TÍRÀ ÁHLÀRÍ (Ẹ̀kọ́ Kẹrin)

فَصْلٌ فِي التَّيَمُّمِ
ÌPÍN TÍ Ó Ń SÀLÀYÉ ÀLÙWÀLÁ ELÉÉPẸ̀ (TÁYÀMỌ́MÙ)

وَيَتَيَمَّمُ الْمُسَافِرُ فِي غَيْرِ مَعْصِيَةٍ، وَالْمَرِيضُ لِفَرِيضَةٍ أَوْ نَافِلَةٍ. وَيَتَيَمَّمُ الْحَاضِرُ الصَّحِيحُ لِلْفَرَائِضِ إِذَا خَافَ خُرُوجَ وَقْتِهَا. وَلَا يَتَيَمَّمُ الْحَاضِرُ الصَّحِيحُ لِنَافِلَةٍ وَلَا جُمُعَةٍ وَلَا جِنَازَةٍ إِلَّا إِذَا تَعَيَّنَتْ عَلَيْهِ الْجَنَازَةُ.

Arìn ìrìn àjó tí ìrìn àjó rẹ̀ kìí se ìrìn àjò ẹ̀sẹ̀, àti aláárẹ̀ lè se àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) láti fi kí ìrun ọ̀ranyàn tàbí àkígbọrẹ (Nááfílà) nígbà tí wọ́n bá se àfẹ́kù omi. Aláìrìnrìn àjò tàbí onílé tí ó dápé, tí ó se àfẹ́kù omi náà lè se àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) láti fi kí ìrun ọ̀ranyàn, nígbà tí ó bá ń bẹ̀rù kí àkókò ìrun má lọ mọ́ ọn lọ́wọ́. Kò sì lẹ́tọ́ fún aláìrìnrìn àjò tàbí onílé tí ó dápé, tí ó se àfẹ́kù omi láti se àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) láti fi kí ìrun àkígbọrẹ (Nááfílà), ìrun Jímọ̀, àti ìrun kiki sí òkú lára. Àyàfi tí kò bá sí ẹlòmíràn tí ó dé ipò kí ó kí ìrun sí òkú lára lẹ́yìn rẹ̀.

(وَفَرَائِضُ التَّيَمُّمِ): النِّيَّةُ وَالصَّعِيدُ الطَّاهِرُ، وَمَسْحُ الْوَجْهِ وَمَسْحُ الْيَدَيْنِ إِلَى الْكُوعَيْنِ، وَضَرْبَةُ الْأَرْضِ الْأُولَى وَالْفَوْرُ، وَدُخُولُ الْوَقْتِ وَاتِّصَالُهُ بِالصَّلَاةِ. وَالصَّعِيدُ هُوَ التُّرَابُ وَالطُّوبُ، وَالْحَجَرُ، وَالثَّلْجُ وَالْخَضْخَاضُ وَنَحْوُ ذَلِكَ. وَلَا يَجُوزُ بِالْجِص اَلْمَطْبُوخِ وَالْحَصِيرِ وَالْخَشَبِ وَالْحَشِيشِ وَنَحْوِهِ، وَرُخِّصَ لِلْمَرِيضِ فِي حَائِطِ الْحَجَرِ وَالطُّوبِ إِنْ لَمْ يَجِدْ مُنَاوِلًا غَيْرَهُ.

Àwọn ọ̀ranyàn àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) ni; (1) Dída àníyàn, (2) Ibi tí ó mọ́ ní ojú ilẹ̀, (3) Pípá ojú, (4) Pípá ọwọ́ méjéèjì títí dé ọrùn ọwọ́, (5) Fífi ọwọ́ lu ilẹ̀ ní ìgbà àkọ́kọ́, (6) Yíyára se àwọn oríké táyàmọ́mù tẹ̀lé ara wọn, (7) Wíwọlé àsìkò ìrun síwájú síse àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù), (8) Síse àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) mọ́ àsìkò ìrun kíkí. Oun tí wọ́n ń pè ní ojú ilẹ̀ ni iyẹ̀ẹ̀pẹ̀, àkàsù iyẹ̀ẹ̀pẹ̀ (Bíríkì), òkuta, yìnyín, iyẹ̀ẹ̀pẹ̀ múlọ́múlọ́, àti àwọn tí ó bá tún rí bíi wọn. Táyàmọ́mù kò sì lẹ́tọ́ síse pẹ̀lú pílásítà, pòpórò ẹní, pákó, igi, koríko, àti àwọn tí ó bá tún rí bíi wọn. Ìgbà láyè wà fún aláìlera kí ó fi ọwọ́ pa ògiri tí wọ́n mọ pẹ̀lú òkuta, àti èyí tí wọ́n fi bíríkì mọ, nígbà tí kò bá rí ǹkan míràn tí ó lè fi se àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) tayọ àwọn ǹkan wọ̀nyí.

(وَسُنَنُهُ): تَجْدِيدُ الصَّعِيدِ لِيَدَيْهِ وَمَسْحُ مَا بَيْنَ الْكُوعَيْنِ وَالْمِرْفَقَيْنَ، وَالتَّرْتِيبُ.

Àwọn ìlànà ànábì lórí ìwẹ̀ àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) ni: (1) Títún ọwọ́ fi kan ojú ilẹ̀ nígbà tí ó bá fẹ́ pá ọwọ́ rẹ̀ méjéèjì, (2) Pípá ọrùn ọwọ́ sí ìgbùnwọ́, (3) Títo àwọn ààyè àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) tẹ̀lé ara wọn, kí ó sì má sé ní pasípayọ.

وَفَضَائِلُهُ التَّسْمِيَةُ وَتَقْدِيمُ الْيُمْنَى عَلَى الْيُسْرَى وَتَقْدِيمُ ظَاهِرِ الذِّرَاعِ عَلَى بَاطِنِهِ وَمُقَدِّمِهِ عَلَى مُؤَخِّرِهِ.

Àwọn oun tí wọ́n fẹ́ síse wọn níbi àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) ni: (1) Bíbẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú orúkọ Ọlọ́hun (Bismillah), (2) Pípá apá ọ̀tún síwájú òsì, (3) Pípá iwájú orí síwájú ẹ̀yìn rẹ̀.

(وَنَوَاقِضُهُ): كَالْوُضُوءِ وَلَا تُصَلَّى فَرِيضَتَانِ بِتَيَمُّمٍ وَاحِدٍ. وَمَنْ تَيَمَّمَ لِفَرِيضَةٍ جَازَ لَهُ النَّوَافِلُ بَعْدَهَا وَمَسُّ الْمُصْحَفِ، وَالطَّوَافُ وَالتِّلَاوَةُ إِنْ نَوَى ذَلِكَ وَاتَّصَلَتْ بِالصَّلَاةِ وَلَمْ يَخْرُجِ الْوَقْتُ، وَجَازَ بِتَيَمُّمِ النَّافِلَةِ كُلُّ مَا ذُكِرَ إِلَّا الْفَرِيضَةَ، وَمَنْ صَلَّى الْعِشَاءَ بِتَيَمُّمٍ قَامَ لِلشَّفْعِ وَالْوَتْرِ بَعْدَهَا مِنْ غَيْرِ تَأْخِيرٍ، وَمَنْ تَيَمَّمَ مِنْ جَنَابَةٍ فَلَا بُدَّ مِنْ نِيَّتِهَا.

Àwọn oun tí ó lè ba Táyàmọ́mù jẹ́ kò yàtọ̀ sí àwọn oun tí ó lè ba àlùwàlá olómi jẹ́. Táyàmọ́mù kan soso kò sì séé fi kí ìrun ọ̀ranyàn méjì papọ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì se táyàmọ́mù fi kí ìrun ọ̀ranyàn kan, ààyè gbà á láti fi yan nafila (Ìrun àkígbọrẹ) lẹ́yìn rẹ̀, àti láti gbá ìwé mímọ́ (Àlùkùráánì) mú, ààyè tún gbà á láti fi pòòrì ilé Ọlọ́hun ni Mákkà (Kàábà), àti láti ka ọ̀rọ̀ Ọlọ́hun (Àlùkùráánì). Lópin ígbà tí ó bá ti da aniyan síse àwọn isẹ́ yìí lasiko tí ó ńse táyàmọ́mù fún ìrun ọ̀ranyàn, tí síse àwọn isẹ́ náà sì bẹ̀rẹ̀ ní kete tí ó kí ìrun ọ̀rànyàn tán, tí àsìkò ìrun ọ̀ranyan tí ó se táyàmọ́mù fún kò sì tíì jáde. Ó lẹ́tọ́ pẹ̀lú kí ó fi táyàmọ́mù tí ó fi sọrí nafila (Ìrun àkígbọrẹ) se àwọn isẹ́ tí wọ̀nyí àyàfi ìrun ọ̀ranyàn. Ẹni tí ó bá fi táyàmọ́mù kí ìrun Ishai lè fi yan nafila (Ìrun àkígbọrẹ) oní méjìméjì (Shafui) àti ẹlẹ́yọkan lẹ́yìn rẹ̀, láì kò fi falẹ̀ rárá. Ẹni tí ó bá sì jẹ́ ẹ̀gbin jánábà tí ó wà lára rẹ̀ ni ó torí rẹ̀ se táyàmọ́mù gbudọ̀ ni àníyàn ìmú ẹ̀gbin jánábà kúrò ní ara láti ìbẹ̀rẹ̀ síse rẹ̀, kí ìrun rẹ̀ lè ní àlààfíà.

Saturday, 14 October 2017

ÌTUMỌ̀ TÍRÀ ÁHLÀRÍ (Ẹ̀kọ́ Kẹta)

فَصْلٌ: يَجِبُ الْغُسْلُ مِنْ ثَلَاثَةِ أَشْيَاءَ: اَلْجَنَابَةِ وَالْحَيْضِ وَالنِّفَاسِ.
فَالْجَنَابَةُ قِسْمَانِ: أَحَدُهُمَا خُرُوجُ الْمَنِيِّ بِلَذَّةٍ مُعْتَادَةٍ فِي نَوْمٍ أَوْ يَقَظَةٍ بِجِمَاعٍ أَوْ غَيْرِهِ. وَالثَّانِي: مَغِيبُ الْحَشَفَةِ فِي الْفَرْجِ. وَمَنْ رَأَى فِي مَنَامِهِ كَأَنَّهُ يُجَامِعُ وَلَمْ يَخْرُجْ مِنْهُ مَنِيٌّ فَلَا شَيْءَ عَلَيْهِ، وَمَنْ وَجَدَ فِي ثَوْبِهِ مَنِيًّا يَابِسًا لَا يَدْرِي مَتَى أَصَابَهُ اغْتَسَلَ وَأَعَادَ مَا صَلَّى مِنْ آخِرِ نَوْمِةٍ نَامَهَا فِيهِ.

Ẹ̀kọ́ míràn: Ìwẹ̀ òfin di ọ̀ranyàn níbi ǹkan mẹ́ta; lílu jánábà, ẹ̀jẹ̀ ǹkan osù obìnrin (Éélà), ẹ̀jẹ̀ ìbimọ (Nìfáásì). Jánábà ní ìpín méjì:
Àkọ́kọ́: jíjáde àtọ̀ (látààrí ìgbadùn tí a ti mọ̀) ní ojú oorun tàbí lójú ayé, kò bá ǹ jẹ́ pẹ̀lú níní àsepọ̀ pẹ̀lú obìnrin tàbí pẹ̀lú ǹkan míràn.
Ìkejì: kí òdiwọ̀n adéńdérí abẹ́ ọkùnrin wọ abẹ́ obìnrin. Ẹni tí ó bá lá àlá tí ó rí ní ojúran wípe òun ń ní àsepọ̀ pẹ̀lú obìnrin tí kò sì rí orípa àtọ̀ nígbà tí ó lajú, kò bùkáátà kí ó wẹ̀ ìwẹ̀ òfin. Ẹni tí ó bá orípa àtọ̀ tí ó ti gbẹ, tí kò mọ ìgbà tí ó jáde lára rẹ̀, ẹni náà yóó wẹ̀, yóò sì dá àwọn ìrun tí ó ti kí láti ẹ̀yìn oorun tí ó sùn gbẹ̀yìn di àkókò tí ó rántí padà.

فَصْلٌ: فَرَائِضُ الْغُسْلِ: النِّيَّةُ عِنْدَ الشُّرُوعِ وَالْفَوْرُ وَالدَّلْكُ وَالْعُمُومُ.

Ẹ̀kọ́ míràn: àwọn ọ̀ranyàn ìwẹ̀ òfin ni; (1) dída àníyàn ní ìbẹ̀rẹ̀ ìwẹ̀, (2) yíyára wẹ̀ ìwẹ̀ òfin, (3) fífi ọwọ́ gbo ara ní àsìkò ìwẹ̀, (4) fífi omi kárí ara.

(وَسُنَنُهُ): غَسْلُ الْيَدَيْنِ إِلَى الْكُوعَيْنِ كَالْوُضُوءِ، وَالْمَضْمَضَةُ وَالِاسْتِنْشَاقُ وَالِاسْتِنْثَارُ، وَغَسْلُ صِمَاخِ الْأُذُنِ وَهِيَ الثُقْبَةُ الدَّاخِلَةُ فِي الرَّأْسِ. وَأَمَّا صَحْفَةُ الْأُذُنِ فَيَجِبُ غَسْلُ ظَاهِرِهَا وَبَاطِنِهَا.

Àwọn ìlànà ànábì lórí ìwẹ̀ òfin ni: (1) wíwẹ ọwọ̀ mèjèèjì títí dé ọrùn ọwọ́ bíi ti àlùwàlá, (2) yíyọ ẹnu, (3) fífín imú, (4) fífọn omi tí a fín sinu ihò imú sí ìta padà, (5) fífọ inú ihò etí. Òun ni ihò tí ó lu já inú agbárí. Ọ̀ranyàn sì ni fífọ inú àti òde ẹ̀rọ etí.

(وَفَضَائِلُهُ): الْبِدَايَةُ بِغَسْلِ النَّجَاسَةِ ثُمَّ الذَّكَرِ فَيَنْوِي عِنْدَهُ، ثُمَّ أَعْضَاءِ الْوُضُوءِ مَرَّةً مَرَّةً، ثُمَّ أَعْلَى جَسَدِهِ، وَتَثْلِيثُ غُسْلِ الرَّأْسِ، وَتَقْدِيمُ شِقِّ جَسَدِهِ الْأَيْمَنِ، وَتَقْلِيلُ الْمَاءِ عَلَى الْأَعْضَاءِ. وَمَنْ نَسِيَ لُمْعَةً أَوْ عُضْوًا مِنْ غُسْلِهِ بَادَرَ إِلَى غَسْلِهِ حِينَ تَذَكُّرِهِ، وَلَوْ بَعْدَ شَهْرٍ، وَأَعَادَ مَا صَلَّى قَبْلَهُ. وَإِنْ أَخَّرَهُ بَعْدَ ذِكْرِهِ بَطَلَ غَسْلُهُ. فَإِنْ كَانَ فِي أَعْضَاءِ الْوُضُوءِ وَصَادَفَهُ غَسْلُ الْوُضُوءِ أَجْزَأَهُ.

Àwọn oun tí wọ́n fẹ́ síse wọn níbi ìwẹ̀ òfin ni: (1) bíbẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú mímú ẹ̀gbin kúrò ní ara, (2) lẹ́yìn náà ni fífọ abẹ́ rẹ̀ (Àsákàrí), níbi fífọ abẹ́ rẹ̀ ni yóò sì ti da àníyàn, (3) lẹ́yìn náà ni síse àwọn iburè àlùwàlá ní ìgbà kọ̀ọ̀kan, (4) lẹ́yìn náà ni wíwẹ òkè ara rẹ̀, (5) fífọ orí ní ìgbà mẹ́ta, (6) wíwẹ abala ọ̀tún ara síwájú abala òsì, (7) lílo omi níwọ̀n níbi wíwẹ̀ àwọn iburè náà. Ẹni tí ó bá gbàgbé wíwẹ̀ ààyè tàbí iburè kan, kí ó yára tete wẹ̀ ẹ́ ní ìgbàkígbà tí ó bá ti rántí, kò bá ǹjẹ́ lẹ́yìn osù kan, kí ó sì san àwọn ìrun tí ó ti kí síwájú rẹ̀. Tí ó bá wáá fi wíwẹ̀ rẹ̀ falẹ̀ lẹ́yìn tí ó ti rántí, ìwẹ̀ òfin tí ó wẹ̀ ti bàjẹ́. Tí ó bá wáá jẹ́ wípé ààyè àlùwàlá ni ó gbàgbé, sùgbọ́n tí omi ìwẹ̀ ti ré kọjá lórí ààyè náà, ìwẹ̀ òfin rẹ̀ kò bàjẹ́.
   
فَصْلٌ: لَا يَحِلُّ لِلْجُنُبِ دُخُولُ الْمَسْجِدِ، وَلَا قِرَاءَةُ الْقُرْآنِ إِلَّا الْآيَةَ وَنَحْوَهَا لِلتَّعَوُّذِ وَنَحْوِهِ. وَلَا يَجُوزُ لِمَنْ لَا يَقْدِرُ عَلَى الْمَاءِ الْبَارِدِ أَنْ يَأْتِيَ زَوْجَتَهُ حَتَّى يُعِدَّ الْآلَةَ إِلَّا أَنْ يَحْتَلِمَ، فَلَا شَيْءَ عَلَيْهِ.  

Ẹ̀kọ́ míràn: kò lẹ́tọ́ fún ẹni tí ó bá ní jánábà lára kí ó wọ ilé ìjọsìn (Masálásí), kò sì lẹ́tọ́ fún un láti ka ọ̀rọ̀ Ọlọ́hun (Àlùkùráánì) àyàfi bíi ẹsẹ kan (aayah) àti oun tí ó bá súnmọ́ ọn tí ó yọ kà láti fi wá ìsọ́ Ọlọ́hun. Kò sì lẹ̀tọ́ fún ẹni tí kò lágbára láti fi omi tutu wẹ̀ kí ó súnmọ́ ìyàwó rẹ̀ titi yóó fi pèsè irin isẹ́ amú omi lọ́ wọ́ọ́rọ́. Àyàfi tí ó bá jẹ́ wípé ó tí lá àlá da ǹkan sí ara tẹ́lẹ̀, kòburú kí ó súnmọ́ ìyàwó rẹ̀. 

Thursday, 12 October 2017

ÌTUMỌ̀ TÍRÀ ÁHLÀRÍ (Ẹ̀kọ́ Kejì)

فَصْلٌ فِي الطَّهَارَةِ
ÌPÍN TÍ Ó Ń SÀLÀYÉ ÌMỌ́TÓTÓ

الطَّهَارَةُ قِسْمَانِ: طَهَارَةُ حَدَثٍ، وَطَهَارَةُ خَبَثٍ، وَلَا يَصِحُّ الْجَمِيعُ إِلَّا بِالْمَاءِ الطَّاهِرِ الْمُطَهِّرِ، وَهُوَ الَّذِي لَمْ يَتَغَيَّرْ لَوْنُهُ أَوْ طَعْمُهُ أَوْ رَائِحَتُهُ بِمَا يُفَارِقُهُ غَالِبًا كَالزَّيْتِ وَالسَّمْنِ وَالدَّسَمِ كُلِّهِ وَالْوَذَحِ وَالصَّابُونِ وَالْوَسَخِ وَنَحْوِهِ، وَلَا بَأْسَ بِالتُّرَابِ وَالْحَمْأَةِ وَالسَّبَخَةِ وَالْآجُرِّ وَنَحْوِهِ.

Ìmọ́tótó pín sí mèjì: Ìmọ́ra níbi ẹ̀gbin, àti íha ẹ̀gbin dànù. Mímú ẹ̀gbin méjéèjì kúrò kò leè ní àlàáfíà àyàfi pẹ̀lu omi tí ó mọ́, tí ó tún le mọ́ ǹkan. Òun (Omi tí ó mọ́, tí ó tún le mọ́ ǹkan) náà ni èyí tí kò yí padà ní ‘Àwọ̀’, tàbí ní ‘Ìtọ́wò’, tàbí ní ‘Òórùn’, pẹ̀lú oun tí ó sepé kò sí nínù àláádà kí ò jẹ́ àbùdá omi tí ó bá dàsí i. Gẹ́gẹ́ bí epo, magarin, gbogbo ìran ọ̀rá, òógùn ìtọ̀ àti ìgbẹ́ ẹranko, ọsẹ, ìdọ̀tí, àti àwọn oun tí ó bá tún dàbí wọn. Kò sí aburu níbi fífi omi tí ó yí padà pẹ̀lú oun tí kìí fi ìgbà kankan yà á se ìmọ́tótó. Gẹ́gẹ́ bì iyẹ̀ẹ̀pẹ̀, amọ̀, ẹrẹ̀, bíríkì, àti àwọn oun tí ó bá jọ wọ́n.

فَصْلٌ: إِذَا تَعَيَّنَتِ النَّجَاسَةُ غُسِلَ مَحَلُّهَا، فَإِنِ الْتَبَسَتْ غُسِلَ الثَّوْبُ كُلُّهُ. وَمَنْ شَكَّ فِي إِصَابَةِ النَّجَاسَةِ نَضَحَ، وَإِنْ أَصَابَهُ شَيْءٌ شَكَّ فِي نَجَاسَتِهِ فَلَا نَضْحَ عَلَيْهِ، وَمَنْ تَذَكَّرَ اَلنَّجَاسَةَ وَهُوَ فِي الصَّلَاةِ قَطَعَ إِلَّا أَنْ يَخَافَ خُرُوجَ الْوَقْتِ. وَمَنْ صَلَّى بِهَا نَاسِيًا وَتَذَكَّرَ بَعْدَ السَّلَامِ أَعَادَ فِي الْوَقْتِ.

Ẹ̀kọ́ Míràn: Tí ààyè ẹ̀gbin bá fojú hàn, ààyè náà di ọ̀ranyàn fífọ̀. Tí ó bá wá dojú rú, odidi asọ dọ̀ranyàn fífọ̀. Ẹni tí ó bá wá ń se iyèméjì lórí pé ẹ̀gbin ta sí ààyè kan, yóò fi omi wọ́n ààyè náà. Tí ó bá wá ń se iyèméjì lórí íjẹ́ ẹ̀gbin oun tí ó ta sí i, kò bùkátà fífi omi wọ́n. Ẹni tí ó bá rántí pé ẹ̀gbin wà lára òun nígbà tí ó ti wà lórí ìrun, ó gbudọ̀ jà ìrun náà, àyàfi tí ó bá ń bẹ̀rù kí àkókò ìrun náà jáde. Ẹni tí ó bá wáá gbàgbé kírun pẹ̀lú ẹ̀gbin lára, tí kò rántí títí tí ó fi mú ìrun náà dópin (Sálámọ̀), ó gbudọ̀ san ìrun náà padà ní àkókò tí ó rántí.

فَصْلٌ: فَرَائِضُ الْوُضُوءِ سَبْعٌ: اَلنِّيَّةُ، وَغَسْلُ الْوَجْهِ، وَغَسْلُ الْيَدَيْنِ إِلَى الْمِرْفَقَيْنِ، وَمَسْحُ الرَّأْسِ، وَغَسْلُ الرِّجْلَيْنِ إِلَى الْكَعْبَيْنِ، وَالدَّلْكُ، وَالْفَوْرُ.

Ẹ̀kọ́ Míràn: Àwọn ọ̀ranyàn àlùwàlá jẹ́ méje- Níní àníyàn, fífọ ojú, wíwẹ ọwọ́ méjéèjì dé ìgbùwọ́, pípá orí, fífọ ẹsẹ̀ méjéèjì dé kókó ẹsẹ̀, fífi ọwọ́ gbo àwọn ààyè náà, síse àwọn ààyè náà láì kò fi àlàfo pípẹ́ sí ààrin wọn.

(وَسُنَنُهُ): غَسْلُ الْيَدَيْنِ إِلَى الْكُوعَيْنِ عِنْدَ الشُّرُوعِ، وَالْمَضْمَضَةُ، وَالِاسْتِنْشَاقُ، وَالِاسْتِنْثَارُ، وَرَدُّ مَسْحِ الرَّأْسِ وَمَسْحُ اَلْأُذُنَيْنِ وَتَجْدِيدُ الْمَاءِ لَهُمَا، وَالتَّرْتِيبُ بَيْنَ الْفَرَائِضِ. وَمَنْ نَسِيَ فَرْضًا مِنْ أَعْضَائِهِ فَإِنْ تَذَكَّرَهُ بِالْقُرْبِ فَعَلَهُ وَمَا بَعْدَهُ، وَإِنْ طَالَ فَعَلَهُ وَحْدَهُ وَأَعَادَ مَا صَلَّى قَبْلَهُ. وَإِنْ تَرَكَ سُنَّةً فَعَلَهَا وَلَا يُعِيدُ الصَّلَاةَ. وَمَنْ نَسِيَ لُمْعَةً غَسَلَهَا وَحْدَهَا بِنِيَّةٍ وَإِنْ صَلَّى قَبْلَ ذَلِكَ أَعَادَ. وَمَنْ تَذَكَّرَ الْمَضْمَضَةَ وَالِاسْتِنْشَاقَ بَعْدَ أَنْ شَرَعَ فِي الْوَجْهِ فَلَا يَرْجِعُ إِلَيْهِمَا حَتَّى يُتِمَّ وُضُوءَهُ.

(Ìlànà Ànábì lórí síse àlùwàlá): fífọ ọwọ́ méjéèjì títí dé ọrùn ọwọ́ ní ìbẹ̀rẹ̀ síse àlùwàlá, yíyọ ẹnu, fífín omi sí imú, fífọn omi tí a fín sinu ihò imú sí ìta padà, dida pípá orí padà láti ẹ̀yìn sí iwájú, pípá etí méjéèjì pẹ̀lú omi ọ̀tun, títò àwọn iburè tí ó jẹ́ ọ̀ranyan tẹ̀lé ara wọn. Ẹni tí ó bá wáá gbàgbé ọ̀kan nínú àwọn iburè tí ó jẹ́ ọ̀ranyàn, tí ó bá yára tete rántí, yóò padà sí ibi iburè náà pẹ̀lú síse àwọn iburè ọ̀ranyàn tí ó tẹ̀le. Tí ó bá wáá pẹ́ kí ó tóó rántí, yóò kàn dá iburè náà se, yóò sì se adápadà ìrun tí ó ti kí. Tí ó bá wáá jẹ́ wípé ọ̀kan nínú àwọn ìlànà síse àlùwàlá tí kìí se ọ̀ranyàn ni ó gbàgbé, yóò kàn se ẹ̀tọ́ tí ó bá yẹ lórí iburè náà, kò sì níí dá ìrun náà padà. Ẹni tí ó bá gbàgbé èkíké iburè àlùwàlá kan, yóò dá iburè náà fọ̀ pẹ̀lú aniyan, koda bí ó bá ti kírun kí ó tóó rántí, yóò dá ìrun náà padà. Ẹni tí ó bá wáá rántí wípé òun kò yọ ẹnu, àti wípé òun kò fín imú, nígbà tí ó ti bẹ̀rẹ̀ orí pípá, kò níí padà sori méjéèjì titi yóò fi parí àlùwàlá rẹ̀.

(وَفَضَائِلُهُ) التَّسْمِيَّةُ وَالسِّوَاكُ وَالزَّائِدُ عَلَى الْغَسْلَةِ الْأُولَى فِي الْوَجْهِ وَالْيَدَيْنِ، وَالْبُدَاءَةُ بِمُقَدِّمِ الرَّأْسِ، وَتَرْتِيبُ السُّنَنِ وَقِلَّةُ الْمَاءِ عَلَى الْعُضْوِ، وَتَقْدِيمُ الْيُمْنَى عَلَى الْيُسْرَى. وَيَجِبُ تَخْلِيلُ أَصَابِعِ الرِّجْلَيْنِ، وَيَجِبُ تَخْلِيلُ اللِّحْيَةِ الْخَفِيفَةِ فِي الْوُضُوءِ دُونَ الْكَثِيفَةِ، وَيَجِبُ تَخْلِيلُهَا فِي الْغُسْلِ وَلَوْ كَانَتْ كَثِيفَةً.

(Àwọn oun tí wọ́n fẹ́ síse wọn níbi àlùwàlá): Dídá orúkọ Ọlọ́hun ní ìbẹ̀rẹ̀ àlùwàlá (Síse Bismillah), rírun orín, fífọ ojú àti ọwọ́ méjéèjì kọjá ẹ̀ẹ̀kan, bíbẹ̀rẹ̀ pípá orí láti iwájú, títo àwọn ìlànà àlùwàlá (Sunan) tẹ̀lé ara wọn, gígán omi lò, síse ìmọ́tótó apá ọ̀tún síwájú apá òsì. Ọ̀ranyàn sì ni fífi ọwọ́ gbo àwọn àlàfo ọmọníka ẹsẹ̀ méjéèjì. Ọ̀ranyàn sì ni fífi ọwọ́ ya irungbọ̀n tí kò bá pọ̀ níbi àlùwàlá, ó sì di ọ̀ranyàn fífi ọwọ́ yà á, kódà kí ó pọ̀ níbi ìwẹ̀ òfin.

فَصْلٌ: نَوَاقِضُ الْوُضُوءِ أَحْدَاثٌ وَأَسْبَابٌ: فَالْأَحْدَاثُ: الْبَوْلُ وَالْغَائِطُ وَالرِّيحُ وَالْمَذْيُ وَالْوَدْيُ. وَالْأَسْبَابُ: النَّوْمُ الثَّقِيلُ وَالْإِغْمَاءُ وَالسُّكْرُ وَالْجُنُونُ وَالْقُبْلَةُ، وَلَمْسُ الْمَرْأَةِ إِنْ قَصَدَ اللَّذَّةَ أَوْ وَجَدَهَا، وَمَسُّ الذَّكَرِ بِبَاطِنِ الْكَفِّ أَوْ بِبَاطِنِ الْأَصَابِعِ. وَمَنْ شَكَّ فِي حَدَثٍ وَجَبَ عَلَيْهِ الْوُضُوءُ إِلَّا أَنْ يَكُونَ مُوَسْوَسًا فَلَا شَيْءَ عَلَيْهِ. وَيَجِبُ عَلَيْهِ غَسْلُ الذَّكَرِ كُلِّهِ مِنَ الْمَذْيِ، وَلَا يَغْسِلُ الْأُنْثَيَيْنِ. وَالْمَذْيُ هُوَ الْمَاءُ الْخَارِجُ عِنْدَ الشَّهْوَةِ الصُّغْرَى بِتَفَكُّرٍ أَوْ نَظَرٍ أَوْ غَيْرِهِ.

Ẹ̀kọ́ míràn: Àwọn oun tí ó má ń ba àlùwàlá ni ẹ̀gbin àti oun tí oun tí ó le se okùnfà ẹ̀gbin. Àwọn ẹ̀gbin tí ó má ń ba àlùwàlá jẹ́ ni: ìtọ̀, ìgbẹ́, isó, àtọ̀ tí ó jáde nígbà tí à ń ronu adùn, àti àtọ̀ tí ó jáde lẹ́yìn ìtọ̀. Àwọn oun tí ó le se okùnfà ẹ̀gbin ni: oorun tí ó wọra, dídákú, ìhúnrìrà, ìpàdánù ọpọlọ, fífi ẹnu ko ẹlẹ́tọ́ ẹni lẹ́nu, dídi obìnrin mú pẹ̀lú èrò adùn tàbí rírí adùn, fífi àtẹlẹwọ́ tàbí ìka di abẹ́ ọkùnrin (àsákàrí) mú. Ẹni tí ó bá se iyèméjì lórí jíjáde ẹ̀gbin lára rẹ̀, síse àlùwàlá di ọ̀ranyàn fún un, àyàfi tí ó bá jẹ́ wípé ó ní àìsàn ròyíròyí, kò níí tún àlùwàlá se. Ó di ọ̀ranyàn fún ẹni ti àtọ̀ jáde lára rẹ̀ nígbà tí ó ń ronu adùn kí ó fọ àsọ̀ọ̀rọ̀ tí ìtọ̀ ńgba jáde, kó sì bùkáátà kí ó fọ àpò kórópọ̀n méjéèjì. Oun tí ń jẹ́ “Mọdiyyu” ni àtọ̀ tí ó ń jáde pẹ̀lú ìrònú tàbí títẹjú mọ́ àti àwọn ǹkan míràn tí ó tún lè mu jáde ní àsìkò adùn kékeré.

فَصْلٌ: لَا يَحِلُّ لِغَيْرِ الْمُتَوَضِّئِ صَلَاةٌ وَلَا طَوَافٌ وَلَا مَسُّ نُسْخَةِ الْقُرْآنِ الْعَظِيمِ وَلَا جِلْدِهَا، لَا بِيَدِهِ وَلَا بِعُودٍ وَنَحَوِهِ إِلَّا الْجُزْءَ مِنْهَا الْمُتَعَلَّمَ فِيهِ، وَلَا مَسُّ لَوْحِ الْقُرْآنِ الْعَظِيمِ عَلَى غَيْرِ الْوُضُوءِ إِلَّا لِمُتَعَلِّمٍ فِيهِ أَوْ مُعَلِّمٍ يُصَحِّحُهُ وَالصَّبِيُّ فِي مَسِّ الْقُرْآنِ كَالْكَبِيرِ، وَالْإِثْمُ عَلَى مُنَاوِلِهِ لَهُ، وَمَنْ صَلَّى بِغَيْرِ وُضُوءٍ عَامِدًا فَهُوَ كَافِرٌ وَالْعِيَاذُ بِاللَّهِ.

Ẹ̀kọ́ míràn: Kò lẹ́tọ́ fún ẹni tí kò ní àlùwàlá kí ó kí ìrun, àti kí ó pòòrì yíká ilé Ọlọ́hun (Kàábà), kò sì ní ẹ̀tọ́ kí ó fi ọ̀kankan nínú oríké ara rẹ̀ gbá odidi àti awọ Àlùkùráánì mú; kò gbudọ̀ fi ọwọ́ kàn án, bẹ́ẹ̀ ni kò gbudọ̀ fi òǹkà (bí igi) àti àwọn oun tí ó bá tún jọ́ kàn án àyàfi tí apá kan láti fi kọ́ ẹ̀kọ́. Kódà dídi pátákó tí wọ́n han Àlùkùráánì sí kò ní ẹ̀tọ́ láì kò ní àlùwàlá, àyàfi fún ẹni tí ó fi ń kọ́ ẹ̀kọ́ tàbí ó fi ń kọ́ ẹlòmíràn ní ẹ̀kọ́. Kò sí ìyàtọ̀ láàrin ọmọdé àti àgbàlagbà níbi ìdájọ́ dídi Àlùkùráánì mú. Ẹni tí yóó sì ni ẹ̀sẹ̀ ni ẹni tí ó bá gbé Àlùkùráánì fún ọmọdé. Ẹni tí ó bá mọ̀ńmọ̀ kí ìrun láì ní àlùwàlá ti di kèfèrí, kí Ọlọ́hun sọ́ wa níbi ìse àti ìwà kèfèrí.

Monday, 9 October 2017

ÌTUMỌ̀ TÍRÀ ÁHLÀRÍ (Ẹ̀kọ́ Kìnní)

Ọ̀RỌ̀ ÌSIWÁJÚ
)تِلْكَ حُدُودُ اللَّهِ فَلَا تَعْتَدُوهَا( [البقرة: 229].
(Àwọn wọ̀n un nì ni ààlà Ọlọ́hun (Allahu), Ẹ má se rékọjá wọn) (Ọgbà Ọ̀rọ̀ Ògédègbe Màálù [Suratu Bakarati], ẹsẹ 229).

بِسْمِ اللَّهِ الرَّحْمَنِ الرَّحِيمِ
اَلْحَمْدُ لِلَّهِ رَبِّ الْعَالَمِينَ، وَالصَّلَاةُ وَالسَّلَامُ عَلَى سَيِّدِنَا مُحَمَّدٍ خَاتَمِ النَّبِيِّينَ وَإِمَامِ الْمُرْسَلِينَ.

Pẹ̀lú orúkọ Ọlọ̀hun Àjọkẹ́ Ayé, Àsàkẹ́ Ọ̀run ni mo fi bẹ̀rẹ̀ ìwé yí. Gbogbo ìran ọpẹ́ jẹ́ ti Ọlọ́hun, Asẹ̀dá gbogbo àgbáńlá ayé. Ìkẹ́ àti ìgẹ̀ kí ó máa bá asíwájú wa Ànábì Muhammadu, ìgbẹ̀yìn gbogbo àwọn ànábì Ọlọ́hun àti asíwájú gbogbo àwọn òjísẹ́ Ọlọ́hun.

(أَوَّلُ مَا يَجِبُ عَلَى الْمُكَلَّفِ): تَصْحِيحُ إِيمَانِهِ ثُمَّ مَعْرِفَةُ مَا يُصْلِحُ بِهِ فَرْضَ عَيْنِهِ كَأَحْكَامِ الصَّلَاةِ وَالطَّهَارَةِ وَالصِّيَامِ.

(Àkọ́kọ́ oun tó pọn dandan fún ẹni tí wọ́n ti la okùn ẹ̀sin bọ̀ lọ́rùn): òun ni síse àtunse ìgbàgbọ́ rẹ̀. Lẹ́yìn náà ni mímọ àwọn oun tí ó le jẹ́ kí àwọn isẹ́ tí ó di ọ̀ranyàn síse fún ẹnìkọ̀ọ̀kan dára. Gẹ́gẹ́ bíi àwọn ìdájọ́ ìrun, ìmọ́tótó, àti ààwẹ̀.

(وَيَجِبُ) عَلَيْهِ أَنْ يُحَافِظَ عَلَى حُدُودِ اللَّهِ وَيَقِفَ عِنْدَ أَمْرِهِ وَنَهْيِهِ وَيَتُوبَ إِلَى اللَّهِ سُبْحَانَهُ قَبْلَ أَنْ يَسْخَطَ عَلَيْهِ.

Ó tún di ọ̀ranyà fún un láti máa kíyèsí àwọn ààlà Ọlọ̀hun, kí ó sì má tayọ àsẹ Ọlọ̀hun, pẹ̀lú kíkóra dúró níbi oun èèwọ̀ rẹ̀. Kí ó sì yára sẹ́rí padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́hun (Túúbá) kí Ó tóó bínù sìi.

(وَشُرُوطُ اَلتَّوْبَةِ) النَّدَمُ عَلَى مَا فَاتَ، وَالنِّيَّةُ أَنْ لَا يَعُودَ إِلَى ذَنْبٍ فِيمَا بَقِيَ عَلَيْهِ مِنْ عُمُرِهِ، وَأَنْ يَتْرُكَ الْمَعْصِيَةَ فِي سَاعَتِهَا إِنْ كَانَ مُتَلَبِّسًا بِهَا، وَلَا يَحِلُّ لَهُ أَنْ يُؤَخِّرَ التَّوْبَةَ، وَلَا يَقُولُ: حَتَّى يَهْدِيَنِي اللَّهُ فَإِنَّهُ مِنْ عَلَامَاتِ الشَّقَاءِ وَالْخِذْلَانِ وَطَمْسِ الْبَصِيرَةِ.

Àwọn májẹ̀mu ìtúúbá náà ni: Ìkábàmọ̀ lórí oun tí ó ti kọjá, ìdàmùrè wípé òun kò níí padà sí ìdí ẹ̀sẹ̀ ní ìgbà tókù tí yóò lò láyé, fífi ìwà ẹ̀sẹ̀ náà sílẹ̀ ní àkókó ìtúúbá tó bá jẹ́ wípé ìwà ẹ̀sẹ̀ náà ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀ lákókò ìtúúbá. Kò sí lẹ́tọ́ fún ẹrú láti fi ìtúúbá falẹ̀. Kí ó jìnnà sí ìmáa sọpé: ó di ìgbà tí Ọlọ́hun bá tọ́mi sọ́nà, nítorípé ìmáa fi ìtúúbá falẹ̀, nínú àmì ‘òfò’, ‘ìpòfo’, àti ‘gbígba ìmọ́lẹ̀ ìgbàgbọ́’ ara ẹni ni.

(وَيَجِبُ) عَلَيْهِ حِفْظُ لِسَانِهِ مِنَ الْفَحْشَاءِ وَالْمُنْكَرِ، وَالْكَلَامِ الْقَبِيحِ، وَأَيْمَانِ الطَّلَاقِ، وَانتْهَارِ الْمُسْلِمِ وَإِهَانَتِهِ، وَسَبِّهِ وَتَخْوِيفِهِ فِي غَيْرِ حَقٍّ شَرْعِيٍّ.

Ó tún di ọ̀ranyàn fún un kí ó máa sọ́ ahọ́n rẹ̀ kùrò níbi àwọn ọ̀rọ̀ àlùfààṣá àti àwọn isẹ́ ẹ̀kọ̀, àwọn ọ̀rọ̀ burúkú àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìbura pẹ̀lú ìkọ̀sílẹ̀, àti ìmaaké mọ́ Mùsùlùmí pẹ̀lu ìyẹpẹrẹ rẹ̀, ìmaa bú Mùsùlùmí àti ìmaa dẹ́rù bàá láì ní ẹ̀tọ́.

(وَيَجِبُ) عَلَيْهِ حِفْظُ بَصَرِهِ عَنِ النَّظَرِ إِلَى الْحَرَامِ، وَلَا يَحِلُّ لَهُ أَنْ يَنْظُرَ إِلَى مُسْلِمٍ بِنَظْرَةٍ تُؤْذِيهِ إِلَّا أَنْ يَكُونَ فَاسِقًا فَيَجِبُ هِجْرَانُهُ.

Ó tún di ọ̀ranyàn le lórí kí ó máa kíyèsí ìríran rẹ̀ níbi mímáa fi wo oun èèwọ̀. Kò sì tún lẹ́tọ́ fún un kí ó máa fi wo Mùsùlùmí ní wiwo tí ó lè pá lára (fojú tẹ́ńbẹ́lú) àyàfi tí ó bá jẹ́ olùfojú sílẹ̀ rọ́lu ẹ̀sẹ̀, ìyàn án lódì yóò jẹ́ ọ̀rayàn le lórí.

(وَيَجِبُ) عَلَيْهِ حِفْظُ جَمِيعِ جَوَارِحِهِ مَا اسْتَطَاعَ، وَأَنْ يُحِبَّ لِلَّهِ وَيُبْغِضَ لَهُ وَيَرْضَى لَهُ وَيَغْضَبَ لَهُ، وَيَأْمُرَ بِالْمَعْرُوفِ وَيَنْهَى عَنِ الْمُنْكَرِ.

Ó tún jẹ́ ọ̀ranyàn fùn un, ìkíyèsí gbogbo àgọ́ ara rẹ̀ pẹ̀lú bí ó bá se ní agbára mọ. Gẹ́gẹ́ bí ó ti se jẹ́ ọ̀ranyàn fún un kí ìfẹ́ níní àti ìkọ̀sílẹ̀ rẹ̀, ìyọ́nú àti ìbínú rẹ̀ máa jẹ́ tori Ọlọ́hun. Ó sì tún di ọ̀ranyàn fún un kí ó máa pàsẹ dáadáa, kí ó sì máa kọ àìdára.

وَيَحْرُمُ عَلَيْهِ الْكَذِبُ وَالْغِيبَةُ وَالنَّمِيمَةُ وَالْكِبْرُ وَالْعُجْبُ وَالرِّيَاءُ وَالسُّمْعَةُ وَالْحَسَدُ وَالْبُغْضُ وَرُؤْيَةُ الْفَضْلِ عَلَى الْغَيْرِ، وَالْهَمْزُ وَاللَّمْزُ وَالْعَبَثُ وَالسُّخْرِيَةُ، وَالزِّنَا، وَالنَّظَرُ إِلَى الْأَجْنَبِيَّةِ، وَالتَّلَذُّذُ بِكَلَامِهَا، وَأَكْلُ أَمْوَالِ النَّاسِ بِغَيْرِ طِيبِ نَفْسٍ وَالْأَكْلُ بِالشَّفَاعَةِ أَوْ بِالدِّينِ وَتَأْخِيرُ الصَّلَاةِ عَنْ أَوْقَاتِهَا. وَلَا يَحِلُّ لَهُ صُحْبَةُ فَاسِقٍ، وَلَا مُجَالَسَتُهُ لِغَيْرِ ضَرُورَةٍ، وَلَا يَطْلُبُ رِضَا الْمَخْلُوقِينَ بِسَخَطِ اَلْخَالِقِ، قَالَ اللَّهُ سُبْحَانَهُ وَتَعَالَى: )وَاللَّهُ وَرَسُولُهُ أَحَقُّ أَنْ يُرْضُوهُ إِنْ كَانُوا مُؤْمِنِينَ(. [التوبة: 62]. وَقَالَ عَلَيْهِ الصَّلَاةُ وَالسَّلَامُ: «لَا طَاعَةَ لِمَخْلُوقٍ فِي مَعْصِيَّةِ الْخَالِقِ».

Èèwọ̀ sì ni ó jẹ́ fún un, irọ́ pipa, ọ̀rọ̀ ẹ̀yìn sísọ, òfófó síse, ìgbéraga, ìjọraẹnilójú, àsehàn, sekágbọ́mi, ìpẹ̀gàn, inúnibíni, ìmaaaripé ènìyàn lọ́lá ju ẹlòmíràn lọ, ìmáabúni loju ẹni, ìmáabúni lẹ́yìn ẹni, ìmaa fẹ̀sìn se awẹ́wa, ìwà àgbèrè, ìmáa tẹjú mọ́ àwọn obìnrin tí kò lẹ́tọ́ sí, ìmáa fi ohùn wọn dọ́fun tòló, ìmáa jẹ dúkìá àwọn èèyàn láì dùn mọ́ wọn nínú, ìmáa fi ìbani wá ìpẹ̀ lọ́dọ̀ Ọlọ́hun tàbí ẹ̀sìn jẹun, ìmáa fi ìrun lọ́ra kọjá àkókò rẹ̀. Kò sì lẹ́tọ́ fún un kí ó máa bá pòkíì èèyàn sọ̀rẹ́, ìmáa jókó pẹ̀lú rẹ̀ láì ní ìdí pàtàkì (Làlúrí).kò sì lẹ́tọ́ fún un kí ó máa wá ìyọ́nú ọmọnìyàn pẹ̀lú ìbínú Ọlọ́hun, nitori ọ̀rọ̀ Ọlọ́hun tí ìtumọ̀ rẹ̀ lọ báyí wípé: (Ọlọ́hun nìkan àti òjísẹ́ rẹ̀ ni lẹ́tọ́ kí wọ́n yọ́ nínú tí ó bá jẹ́ wípé olùgbàgbọ́ tòótọ́ ni wọ́n jẹ́) (Ọgbà Ọ̀rọ̀ Ìtúúbá [Suratut Taobati], ẹsẹ 62). Ànábì (kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa báa) náà tún sọ wípé: “Ìtẹ̀lé éyíkéyí nínú àwọn ẹ̀dá níbi oun tí ó le múni sẹ Ọlọ́hun adẹ́dá, kò lẹ́tọ́”.

وَلَا يَحِلُّ لَهُ أَنْ يَفْعَلَ فِعْلًا حَتَّى يَعْلَمَ حُكْمَ اللَّهِ فِيهِ وَيَسْأَلَ الْعُلَمَاءَ وَيَقْتَدِيَ بِالْمُتَّبِعِينَ لِسُنَّةِ مُحَمَّدٍ صَلَّى اللَّهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ اَلَّذِينَ يَدُلُّونَ عَلَى طَاعَةِ اللَّهِ، وَيُحَذِّرُونَ مِنَ اتِّبَاعِ الشَّيْطَانِ.

Kò tún tọ́ fún ẹni tí wọ́n ti lakùn ẹ̀sìn bọ̀ lọ́rùn kí ó se isẹ́ kan títí yóò fi mọ ìdájọ́ Ọlọ́hun lórí rẹ̀, tí yóò sì fi bi àwọn olùmọ̀ ẹ̀sìn léèrè nípa rẹ̀, tí yóò sì kọ́se àwọn tí ó bá ń tẹ̀lé ìlànà Ànábì (kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa báa) nínú wọn, àwọn tí wọ́n máá ń tọ́ka èèyàn sí ìtẹ̀lé Ọlọ́hun, tí wọn sì máá ń ki èèyàn nílọ̀ níbi ìtẹ̀lé ìlànà èsù (Sètáánì).

 وَلَا يَرْضَى لِنَفْسِهِ مَا رَضِيَهُ الْمُفْلِسُونَ الَّذِينَ ضَاعَتْ أَعْمَارُهُمْ فِي غَيْرِ طَاعَةِ اللَّهِ تَعَالَى، فَيَا حَسْرَتَهُمْ وَيَا طُولَ بُكَائِهِمْ يَوْمَ الْقِيَامَةِ، نَسْأَلُ اللَّهَ أَنْ يُوَفِّقَنَا لِاتِّبَاعِ سُنَّةِ نَبِيِّنَا وَشَفِيعِنَا وَسَيِّدِنَا مُحَمَّدٍ صَلَّى اللَّهُ عَلَيْهِ وَسَلَّمَ.

Ẹni tí wọ́n ti la okun ẹ̀sìn bọ̀ lọ́rùn kò sì gbudọ̀ jẹ́ ẹni tí ó jẹ́ pé oun tí yóò maa dá lọ́rùn ni oun tí ó bá ń dá pòkíì (Aláse dànù) lọ́rùn, àwọn tí wọ́n se ọjọ́ ayé wọn lófò lórí oun tí ó yàtọ̀ sí ìtẹ̀lé Ọlọ́hun. Báwo ni àbámọ̀ wọn yóò se tó, bawo ni ẹkún wọn yóò se pọ̀ tó lọ́jọ́ ìgbéǹde àlùkìyáómọ. À ń bẹ Ọlọ́hun (Allahu) kí ó fi wá se kòǹgẹ́ ìtẹ̀lé ìlànà Ànábì, Olùsìpẹ̀, àti Asíwájú wa Muhammadu kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa báa.

Saturday, 7 October 2017

ÌTUMỌ̀ TÍRÀ ÁHLÀRÍ



ÌTUMỌ̀
ÌWÉ ÌKỌNILẸ́KỌ́ Ẹ̀SÌN NÍ ÌLÀNÀ TI ÌMÁMÙ MAALIKU ỌMỌ ANASI 

TÍ Ó GBAJÚMỌ̀ SÍ (AL ÁHLÀRÍYYU)

TI
ÀGBÀ ÒǸKỌ̀WÉ, ONÍMÍMỌ̀
ABDUL RAHMAN ỌMỌ MUHAMMADU AS SAGEERI (AL AHLARIYYU)


SÍ ÈDÈ YORÙBÁ
LÁTI ỌWỌ́ AKẸ́KỌ́ Ẹ̀SÌN KAN


The timeless lessons from Abū Bakr’s companionship with the Prophet ﷺ during the migration to Madinah

  كِتَابُ فَضَائِلِ الصَّحَابَةِ مَنَاقِبُ أَبِي بَكْرٍ رَضِي عَنْهُ بَابُ قَوْلِهِ تَعَالَى: ﴿إِذْ يَقُولُ لِصَاحِبِهِ لَا تَحْزَنْ إِنَّ ا...