Friday, 20 October 2017

ÌTUMỌ̀ TÍRÀ ÁHLÀRÍ (Ẹ̀kọ́ Kẹrin)

فَصْلٌ فِي التَّيَمُّمِ
ÌPÍN TÍ Ó Ń SÀLÀYÉ ÀLÙWÀLÁ ELÉÉPẸ̀ (TÁYÀMỌ́MÙ)

وَيَتَيَمَّمُ الْمُسَافِرُ فِي غَيْرِ مَعْصِيَةٍ، وَالْمَرِيضُ لِفَرِيضَةٍ أَوْ نَافِلَةٍ. وَيَتَيَمَّمُ الْحَاضِرُ الصَّحِيحُ لِلْفَرَائِضِ إِذَا خَافَ خُرُوجَ وَقْتِهَا. وَلَا يَتَيَمَّمُ الْحَاضِرُ الصَّحِيحُ لِنَافِلَةٍ وَلَا جُمُعَةٍ وَلَا جِنَازَةٍ إِلَّا إِذَا تَعَيَّنَتْ عَلَيْهِ الْجَنَازَةُ.

Arìn ìrìn àjó tí ìrìn àjó rẹ̀ kìí se ìrìn àjò ẹ̀sẹ̀, àti aláárẹ̀ lè se àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) láti fi kí ìrun ọ̀ranyàn tàbí àkígbọrẹ (Nááfílà) nígbà tí wọ́n bá se àfẹ́kù omi. Aláìrìnrìn àjò tàbí onílé tí ó dápé, tí ó se àfẹ́kù omi náà lè se àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) láti fi kí ìrun ọ̀ranyàn, nígbà tí ó bá ń bẹ̀rù kí àkókò ìrun má lọ mọ́ ọn lọ́wọ́. Kò sì lẹ́tọ́ fún aláìrìnrìn àjò tàbí onílé tí ó dápé, tí ó se àfẹ́kù omi láti se àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) láti fi kí ìrun àkígbọrẹ (Nááfílà), ìrun Jímọ̀, àti ìrun kiki sí òkú lára. Àyàfi tí kò bá sí ẹlòmíràn tí ó dé ipò kí ó kí ìrun sí òkú lára lẹ́yìn rẹ̀.

(وَفَرَائِضُ التَّيَمُّمِ): النِّيَّةُ وَالصَّعِيدُ الطَّاهِرُ، وَمَسْحُ الْوَجْهِ وَمَسْحُ الْيَدَيْنِ إِلَى الْكُوعَيْنِ، وَضَرْبَةُ الْأَرْضِ الْأُولَى وَالْفَوْرُ، وَدُخُولُ الْوَقْتِ وَاتِّصَالُهُ بِالصَّلَاةِ. وَالصَّعِيدُ هُوَ التُّرَابُ وَالطُّوبُ، وَالْحَجَرُ، وَالثَّلْجُ وَالْخَضْخَاضُ وَنَحْوُ ذَلِكَ. وَلَا يَجُوزُ بِالْجِص اَلْمَطْبُوخِ وَالْحَصِيرِ وَالْخَشَبِ وَالْحَشِيشِ وَنَحْوِهِ، وَرُخِّصَ لِلْمَرِيضِ فِي حَائِطِ الْحَجَرِ وَالطُّوبِ إِنْ لَمْ يَجِدْ مُنَاوِلًا غَيْرَهُ.

Àwọn ọ̀ranyàn àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) ni; (1) Dída àníyàn, (2) Ibi tí ó mọ́ ní ojú ilẹ̀, (3) Pípá ojú, (4) Pípá ọwọ́ méjéèjì títí dé ọrùn ọwọ́, (5) Fífi ọwọ́ lu ilẹ̀ ní ìgbà àkọ́kọ́, (6) Yíyára se àwọn oríké táyàmọ́mù tẹ̀lé ara wọn, (7) Wíwọlé àsìkò ìrun síwájú síse àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù), (8) Síse àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) mọ́ àsìkò ìrun kíkí. Oun tí wọ́n ń pè ní ojú ilẹ̀ ni iyẹ̀ẹ̀pẹ̀, àkàsù iyẹ̀ẹ̀pẹ̀ (Bíríkì), òkuta, yìnyín, iyẹ̀ẹ̀pẹ̀ múlọ́múlọ́, àti àwọn tí ó bá tún rí bíi wọn. Táyàmọ́mù kò sì lẹ́tọ́ síse pẹ̀lú pílásítà, pòpórò ẹní, pákó, igi, koríko, àti àwọn tí ó bá tún rí bíi wọn. Ìgbà láyè wà fún aláìlera kí ó fi ọwọ́ pa ògiri tí wọ́n mọ pẹ̀lú òkuta, àti èyí tí wọ́n fi bíríkì mọ, nígbà tí kò bá rí ǹkan míràn tí ó lè fi se àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) tayọ àwọn ǹkan wọ̀nyí.

(وَسُنَنُهُ): تَجْدِيدُ الصَّعِيدِ لِيَدَيْهِ وَمَسْحُ مَا بَيْنَ الْكُوعَيْنِ وَالْمِرْفَقَيْنَ، وَالتَّرْتِيبُ.

Àwọn ìlànà ànábì lórí ìwẹ̀ àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) ni: (1) Títún ọwọ́ fi kan ojú ilẹ̀ nígbà tí ó bá fẹ́ pá ọwọ́ rẹ̀ méjéèjì, (2) Pípá ọrùn ọwọ́ sí ìgbùnwọ́, (3) Títo àwọn ààyè àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) tẹ̀lé ara wọn, kí ó sì má sé ní pasípayọ.

وَفَضَائِلُهُ التَّسْمِيَةُ وَتَقْدِيمُ الْيُمْنَى عَلَى الْيُسْرَى وَتَقْدِيمُ ظَاهِرِ الذِّرَاعِ عَلَى بَاطِنِهِ وَمُقَدِّمِهِ عَلَى مُؤَخِّرِهِ.

Àwọn oun tí wọ́n fẹ́ síse wọn níbi àlùwàlá eléépẹ̀ (Táyàmọ́mù) ni: (1) Bíbẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú orúkọ Ọlọ́hun (Bismillah), (2) Pípá apá ọ̀tún síwájú òsì, (3) Pípá iwájú orí síwájú ẹ̀yìn rẹ̀.

(وَنَوَاقِضُهُ): كَالْوُضُوءِ وَلَا تُصَلَّى فَرِيضَتَانِ بِتَيَمُّمٍ وَاحِدٍ. وَمَنْ تَيَمَّمَ لِفَرِيضَةٍ جَازَ لَهُ النَّوَافِلُ بَعْدَهَا وَمَسُّ الْمُصْحَفِ، وَالطَّوَافُ وَالتِّلَاوَةُ إِنْ نَوَى ذَلِكَ وَاتَّصَلَتْ بِالصَّلَاةِ وَلَمْ يَخْرُجِ الْوَقْتُ، وَجَازَ بِتَيَمُّمِ النَّافِلَةِ كُلُّ مَا ذُكِرَ إِلَّا الْفَرِيضَةَ، وَمَنْ صَلَّى الْعِشَاءَ بِتَيَمُّمٍ قَامَ لِلشَّفْعِ وَالْوَتْرِ بَعْدَهَا مِنْ غَيْرِ تَأْخِيرٍ، وَمَنْ تَيَمَّمَ مِنْ جَنَابَةٍ فَلَا بُدَّ مِنْ نِيَّتِهَا.

Àwọn oun tí ó lè ba Táyàmọ́mù jẹ́ kò yàtọ̀ sí àwọn oun tí ó lè ba àlùwàlá olómi jẹ́. Táyàmọ́mù kan soso kò sì séé fi kí ìrun ọ̀ranyàn méjì papọ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì se táyàmọ́mù fi kí ìrun ọ̀ranyàn kan, ààyè gbà á láti fi yan nafila (Ìrun àkígbọrẹ) lẹ́yìn rẹ̀, àti láti gbá ìwé mímọ́ (Àlùkùráánì) mú, ààyè tún gbà á láti fi pòòrì ilé Ọlọ́hun ni Mákkà (Kàábà), àti láti ka ọ̀rọ̀ Ọlọ́hun (Àlùkùráánì). Lópin ígbà tí ó bá ti da aniyan síse àwọn isẹ́ yìí lasiko tí ó ńse táyàmọ́mù fún ìrun ọ̀ranyàn, tí síse àwọn isẹ́ náà sì bẹ̀rẹ̀ ní kete tí ó kí ìrun ọ̀rànyàn tán, tí àsìkò ìrun ọ̀ranyan tí ó se táyàmọ́mù fún kò sì tíì jáde. Ó lẹ́tọ́ pẹ̀lú kí ó fi táyàmọ́mù tí ó fi sọrí nafila (Ìrun àkígbọrẹ) se àwọn isẹ́ tí wọ̀nyí àyàfi ìrun ọ̀ranyàn. Ẹni tí ó bá fi táyàmọ́mù kí ìrun Ishai lè fi yan nafila (Ìrun àkígbọrẹ) oní méjìméjì (Shafui) àti ẹlẹ́yọkan lẹ́yìn rẹ̀, láì kò fi falẹ̀ rárá. Ẹni tí ó bá sì jẹ́ ẹ̀gbin jánábà tí ó wà lára rẹ̀ ni ó torí rẹ̀ se táyàmọ́mù gbudọ̀ ni àníyàn ìmú ẹ̀gbin jánábà kúrò ní ara láti ìbẹ̀rẹ̀ síse rẹ̀, kí ìrun rẹ̀ lè ní àlààfíà.

No comments:

The timeless lessons from Abū Bakr’s companionship with the Prophet ﷺ during the migration to Madinah

  كِتَابُ فَضَائِلِ الصَّحَابَةِ مَنَاقِبُ أَبِي بَكْرٍ رَضِي عَنْهُ بَابُ قَوْلِهِ تَعَالَى: ﴿إِذْ يَقُولُ لِصَاحِبِهِ لَا تَحْزَنْ إِنَّ ا...