Ọ̀rọ̀ Olùkọ̀wé Ní Èdè Lárúbáwá
قَالَ الشَّافِعِيُّ -رَحِمَهُ
اللهُ تَعَالَى-: "لَوْ مَا أَنْزَلَ اللهُ حُجَّةً عَلَى خَلْقِهِ إِلَّا َهذِهِ
السُّورَةَ لَكَفَتْهُم.
وَالدَّلِيلُ قَوْلُهُ تَعَالَى:
﴿فَاعْلَمْ أَنَّهُ لَا إِلَهَ إِلَّا اللَّهُ
وَاسْتَغْفِرْ لِذَنْبِكَ وَلِلْمُؤْمِنِينَ وَالْمُؤْمِنَات وَاللَّهُ يَعْلَمُ
مُتَقَلَّبَكُمْ وَمَثْوَاكُمْ﴾ [محمد: 19]. فَبَدَأَ بِالْعِلَمِ قَبْلَ
الْقَوْلِ وَالْعَمَلِ.
ÌTUMỌ̀
Olùmọ̀ Àgbà, Asíwájú Ṣafiiyu –kí Ọlọ́hun lékún ìkẹ́ wọn- sọpé:
“tí Ọlọ́hun Ọba (Allahu) kò bá sọ ọgbà ọ̀rọ̀ (Suuratu) míràn kalẹ̀ fún àwọn ẹ́dá
rẹ̀ lòrí àwọn ìpìlẹ̀ mẹ́ẹ́rẹ̀rin yìí tó kọjá eléyìí, ó ti tó fún wọn”.
Olùmọ̀ Àgbà, Asíwájú Buhariyyu - kí Ọlọ́hun lékún ìkẹ́ wọn-
náà tún fi se àkọlé ẹsẹ ọ̀rọ̀ Ọlọ́hun (Aayatu) tó ń bọ̀ yìí, ọ́rọ̀ rẹ̀ tó sọ pé:
“ákórí ẹsẹ ọ̀rọ̀ (Aayatu) tó ń bọ̀ yí ni wípé: ìmọ̀ gbudọ̀ síwájú èyíkéyí ọ̀rọ̀
àti ìse”. Ẹ̀rí eléyí sì ni ọ̀rọ̀ Ọlọ́hun tí ìtumọ̀ rẹ̀ lọ báyí wípé: (Kọ́kọ́ lọrèémọ̀ wípé kò sí ẹnikẹ́ni tó lẹ́tọ́ sí ìjọsìn òdodo
yàtọ̀ sí Ọlọ́hun (Allahu), lẹ́yìn náà kí o máa wá àforíjìn ẹ̀sẹ̀ fún ara rẹ àti
fún gbogbo ódodo lọ́kùnrin àti lóbìnrin). Èyí nipé, Ọlọ́hun (Allahu) fi ìmọ̀ siwájú ọ̀rọ̀ àti íse.

No comments:
Post a Comment